-
‘A ó Fìdí Àwọn Ìwéwèé Rẹ Múlẹ̀ Gbọn-in Gbọn-in’Ilé Ìṣọ́—2007 | May 15
-
-
NÍNÚ orin kan tí onísáàmù náà Dáfídì kọ, ó gbàdúrà pé: “Àní kí o dá ọkàn-àyà mímọ́ gaara sínú mi, Ọlọ́run, kí o sì fi ẹ̀mí tuntun sínú mi, ọ̀kan tí ó fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin. Mú ayọ̀ ńláǹlà ìgbàlà rẹ padà bọ̀ sípò fún mi, kí o sì fi ẹ̀mí ìmúratán pàápàá tì mí lẹ́yìn.” (Sáàmù 51:10, 12) Lẹ́yìn tí Dáfídì dẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú Bátí-ṣébà, ó bẹ Jèhófà Ọlọ́run nínú ẹsẹ Bíbélì yìí pé kó fọ ọkàn òun mọ́ kó sì fi ẹ̀mí ṣíṣe ohun tó dára sínú òun.
Ṣé Jèhófà máa ń dá ọkàn tuntun sínú wa ni, bóyá tó tiẹ̀ tún ń fi ẹ̀mí tuntun àti ẹ̀mí ìmúratán sínú wa? Àbí a ní láti sapá ká tó lè ní ọkàn mímọ́ ká má sì jẹ́ kó padà di aláìmọ́? Lóòótọ́, “Jèhófà ni olùṣàyẹ̀wò àwọn ọkàn-àyà,” àmọ́, báwo ló ṣe ń lọ́wọ́ sí ohun tó ń lọ nínú ọkàn wa tó? (Òwe 17:3; Jeremáyà 17:10) Báwo ló sì ṣe ń darí ìgbésí ayé wa tó, àti ìwà wa àtohun tó ń mú wa ṣe àwọn nǹkan?
-
-
‘A ó Fìdí Àwọn Ìwéwèé Rẹ Múlẹ̀ Gbọn-in Gbọn-in’Ilé Ìṣọ́—2007 | May 15
-
-
Ta Ló Ń ‘Ṣètò Ọkàn-Àyà’?
Apá àkọ́kọ́ nínú Òwe orí kẹrìndínlógún ẹsẹ kìíní sọ pé: “Àwọn ìṣètò ọkàn-àyà jẹ́ ti ará ayé.” Èyí fi hàn pé ojúṣe wa ni láti ‘ṣètò ọkàn’ wa. Jèhófà kì í fúnra rẹ̀ bá wa ṣètò ọkàn wa, bẹ́ẹ̀ sì ni kì í gbé ẹ̀mí ìmúratán wọ̀ wá. A ní láti sapá láti ní ìmọ̀ Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ́nà pípéye, ká ronú lórí ohun tá a bá kọ́ nínú rẹ̀, ká sì jẹ́ kí èrò wa bá ti Jèhófà mu.—Òwe 2:10, 11.
Àmọ́, bí Dáfídì ṣe ní kí Jèhófà dá “ọkàn-àyà mímọ́ gaara” sínú òun kó sì fi “ẹ̀mí tuntun” sínú òun fi hàn pé ó mọ̀ pé ẹni tó lè dẹ́ṣẹ̀ lòun, àti pé òun nílò ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run láti lè fọ ọkàn òun mọ́. Níwọ̀n bá a ti jẹ́ aláìpé, a lè rí ìdẹwò tó máa fẹ́ mú wa lọ́wọ́ nínú “àwọn iṣẹ́ ti ara.” (Gálátíà 5:19-21) A nílò ìrànlọ́wọ́ Jèhófà láti lè “sọ àwọn ẹ̀yà ara [wa] tí ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé di òkú ní ti àgbèrè, ìwà àìmọ́, ìdálọ́rùn fún ìbálòpọ̀ takọtabo, ìfẹ́-ọkàn tí ń ṣeni lọ́ṣẹ́, àti ojúkòkòrò.” (Kólósè 3:5) Ó ṣe pàtàkì gan-an ni pé ká máa gbàdúrà pé kí Jèhófà ràn wá lọ́wọ́ ká má bàa juwọ́ sílẹ̀ fún ìdẹwò ká sì lè mú àwọn ohun tó lè mú wa dẹ́ṣẹ̀ kúrò lọ́kàn wa!
-