ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ‘A ó Fìdí Àwọn Ìwéwèé Rẹ Múlẹ̀ Gbọn-in Gbọn-in’
    Ilé Ìṣọ́—2007 | May 15
    • NÍNÚ orin kan tí onísáàmù náà Dáfídì kọ, ó gbàdúrà pé: “Àní kí o dá ọkàn-àyà mímọ́ gaara sínú mi, Ọlọ́run, kí o sì fi ẹ̀mí tuntun sínú mi, ọ̀kan tí ó fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin. Mú ayọ̀ ńláǹlà ìgbàlà rẹ padà bọ̀ sípò fún mi, kí o sì fi ẹ̀mí ìmúratán pàápàá tì mí lẹ́yìn.” (Sáàmù 51:10, 12) Lẹ́yìn tí Dáfídì dẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú Bátí-ṣébà, ó bẹ Jèhófà Ọlọ́run nínú ẹsẹ Bíbélì yìí pé kó fọ ọkàn òun mọ́ kó sì fi ẹ̀mí ṣíṣe ohun tó dára sínú òun.

      Ṣé Jèhófà máa ń dá ọkàn tuntun sínú wa ni, bóyá tó tiẹ̀ tún ń fi ẹ̀mí tuntun àti ẹ̀mí ìmúratán sínú wa? Àbí a ní láti sapá ká tó lè ní ọkàn mímọ́ ká má sì jẹ́ kó padà di aláìmọ́? Lóòótọ́, “Jèhófà ni olùṣàyẹ̀wò àwọn ọkàn-àyà,” àmọ́, báwo ló ṣe ń lọ́wọ́ sí ohun tó ń lọ nínú ọkàn wa tó? (Òwe 17:3; Jeremáyà 17:10) Báwo ló sì ṣe ń darí ìgbésí ayé wa tó, àti ìwà wa àtohun tó ń mú wa ṣe àwọn nǹkan?

  • ‘A ó Fìdí Àwọn Ìwéwèé Rẹ Múlẹ̀ Gbọn-in Gbọn-in’
    Ilé Ìṣọ́—2007 | May 15
    • Ta Ló Ń ‘Ṣètò Ọkàn-Àyà’?

      Apá àkọ́kọ́ nínú Òwe orí kẹrìndínlógún ẹsẹ kìíní sọ pé: “Àwọn ìṣètò ọkàn-àyà jẹ́ ti ará ayé.” Èyí fi hàn pé ojúṣe wa ni láti ‘ṣètò ọkàn’ wa. Jèhófà kì í fúnra rẹ̀ bá wa ṣètò ọkàn wa, bẹ́ẹ̀ sì ni kì í gbé ẹ̀mí ìmúratán wọ̀ wá. A ní láti sapá láti ní ìmọ̀ Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ́nà pípéye, ká ronú lórí ohun tá a bá kọ́ nínú rẹ̀, ká sì jẹ́ kí èrò wa bá ti Jèhófà mu.—Òwe 2:10, 11.

      Àmọ́, bí Dáfídì ṣe ní kí Jèhófà dá “ọkàn-àyà mímọ́ gaara” sínú òun kó sì fi “ẹ̀mí tuntun” sínú òun fi hàn pé ó mọ̀ pé ẹni tó lè dẹ́ṣẹ̀ lòun, àti pé òun nílò ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run láti lè fọ ọkàn òun mọ́. Níwọ̀n bá a ti jẹ́ aláìpé, a lè rí ìdẹwò tó máa fẹ́ mú wa lọ́wọ́ nínú “àwọn iṣẹ́ ti ara.” (Gálátíà 5:19-21) A nílò ìrànlọ́wọ́ Jèhófà láti lè “sọ àwọn ẹ̀yà ara [wa] tí ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé di òkú ní ti àgbèrè, ìwà àìmọ́, ìdálọ́rùn fún ìbálòpọ̀ takọtabo, ìfẹ́-ọkàn tí ń ṣeni lọ́ṣẹ́, àti ojúkòkòrò.” (Kólósè 3:5) Ó ṣe pàtàkì gan-an ni pé ká máa gbàdúrà pé kí Jèhófà ràn wá lọ́wọ́ ká má bàa juwọ́ sílẹ̀ fún ìdẹwò ká sì lè mú àwọn ohun tó lè mú wa dẹ́ṣẹ̀ kúrò lọ́kàn wa!

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́