-
Jèhófà Ń fi Bí a ó Ṣe Máa Ka Àwọn Ọjọ́ Wa Hàn WáIlé Ìṣọ́—2001 | November 15
-
-
4-6. Báwo ni Jèhófà ṣe jẹ́ “ibùgbé gidi” fún wa?
4 Onísáàmù náà gbẹ́nu lé ọ̀rọ̀, ó ní: “Jèhófà, ìwọ tìkára rẹ ti jẹ́ ibùgbé gidi fún wa ní ìran dé ìran. Àní kí a tó bí àwọn òkè ńlá, tàbí kí o tó bẹ̀rẹ̀ sí bí ilẹ̀ ayé àti ilẹ̀ eléso gẹ́gẹ́ bí ẹni pé pẹ̀lú ìrora ìrọbí, àní láti àkókò tí ó lọ kánrin títí dé àkókò tí ó lọ kánrin, ìwọ ni Ọlọ́run [tàbí, Olú Ọ̀run].”—Sáàmù 90:1, 2, àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé, NW.
-
-
Jèhófà Ń fi Bí a ó Ṣe Máa Ka Àwọn Ọjọ́ Wa Hàn WáIlé Ìṣọ́—2001 | November 15
-
-
7. Lọ́nà wo la gbà “bí” àwọn òkè ńlá, tá a sì mú ilẹ̀ ayé jáde gẹ́gẹ́ bí ẹni pé pẹ̀lú “ìrora ìrọbí”?
7 Jèhófà ti wà kí a tó “bí” àwọn òkè ńlá, tàbí kí a tó mú ilẹ̀ ayé jáde gẹ́gẹ́ bí ẹni pé pẹ̀lú “ìrora ìrọbí.” Tá a bá fi ojú èèyàn wò ó, kékeré kọ́ ni iṣẹ́ dídá ilẹ̀ ayé yìí, pẹ̀lú gbogbo nǹkan fífanimọ́ra tí ń bẹ nínú rẹ̀, àwọn èròjà inú rẹ̀, àtàwọn ètò ìṣiṣẹ́ rẹ̀ dídíjú. Nígbà tí onísáàmù náà sì sọ pé a “bí” àwọn òkè ńlá àti pé a mú ilẹ̀ ayé jáde gẹ́gẹ́ bí ẹni pé pẹ̀lú “ìrora ìrọbí,” ńṣe ló ń fi ìmọrírì ńlá hàn fún iṣẹ́ ribiribi tí Jèhófà ṣe nígbà tó dá nǹkan wọ̀nyí. Ǹjẹ́ kò yẹ kí àwa náà ní irú ọ̀wọ̀ àti ìmọrírì bẹ́ẹ̀ fún iṣẹ́ Ẹlẹ́dàá?
Jèhófà Kò Fi Wá Sílẹ̀ Rí
8. Kí ni gbólóhùn náà pé Jèhófà ni Ọlọ́run “láti àkókò tí ó lọ kánrin títí dé àkókò tí ó lọ kánrin” túmọ̀ sí?
8 Onísáàmù náà kọ ọ́ lórin pé: “Àní láti àkókò tí ó lọ kánrin títí dé àkókò tí ó lọ kánrin, ìwọ ni Ọlọ́run.” “Àkókò tí ó lọ kánrin” lè tọ́ka sí àwọn nǹkan tó lópin, àmọ́ tí a kò mọ àkókò pàtó tó máa dópin. (Ẹ́kísódù 31:16, 17; Hébérù 9:15) Ṣùgbọ́n ní Sáàmù 90:2 àti láwọn ibòmíràn nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù, “àkókò tí ó lọ kánrin” túmọ̀ sí “ayérayé.” (Oníwàásù 1:4) Àlàyé náà pé Ọlọ́run ti wà láti ayérayé, kọjá ohun tí òye wa lè gbé. Síbẹ̀, Jèhófà kò ní ìbẹ̀rẹ̀, kò sì ní lópin. (Hábákúkù 1:12) Títí ayé ni yóò máa wà, tí yóò sì máa ràn wá lọ́wọ́.
-