-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Ẹ wo báa ti ṣe lè kún fún ìmoore tó pé ọgbọ́n tòótọ́ àti àwọn ànímọ́ tó tan mọ́ ọn tún ń dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin àti obìnrin oníṣekúṣe! Sólómọ́nì fi kún un pé àwọn ànímọ́ wọ̀nyí wà “láti dá ọ nídè kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin, kúrò lọ́wọ́ obìnrin ilẹ̀ òkèèrè tí ó ti mú kí àwọn àsọjáde rẹ̀ dùn mọ̀nràn-ìn mọnran-in, ẹni tí ń fi ọ̀rẹ́ àfinúhàn ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì ti gbàgbé májẹ̀mú Ọlọ́run rẹ̀. Nítorí inú ikú nísàlẹ̀ ni ilé rẹ̀ rì sí àti sí ìsàlẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ó jẹ́ aláìlè-ta-pútú nínú ikú ni àwọn òpó ọ̀nà rẹ̀. Kò sí ìkankan lára àwọn tí ń ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ tí yóò padà wá, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò tún padà rí ipa ọ̀nà àwọn alààyè.”—Òwe 2:16-19.
“Àjèjì obìnrin,” ìyẹn ni aṣẹ́wó, la sọ̀rọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹni tó fi “ọ̀rẹ́ àfinúhàn ìgbà èwe rẹ̀” sílẹ̀—ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ọkọ tó fẹ́ ẹ́ lọ́lọ́mọge.a (Fi wé Málákì 2:14.) Ó ti gbàgbé pé májẹ̀mú Òfin ka panṣágà léèwọ̀. (Ẹ́kísódù 20:14) Ọ̀nà ikú lọ́nà rẹ̀. Àwọn tó bá sì ń bá a ṣe wọléwọ̀de kò ní “padà rí ipa ọ̀nà àwọn alààyè” láé, torí pé bó pẹ́ bó yá wọ́n lè kàndin nínú iyọ̀ nípa rírìn débi tí iwájú ò ti ní ṣeé lọ, tí ẹ̀yìn ò ti ní ṣeé padà sí, kí wọ́n sì tibẹ̀ ríkú he. Ọkùnrin tó lóye, tí agbára ìrònú rẹ̀ sì jí pépé yóò tètè fura, kò ní kó sínú àwọn ọ̀fìn ìṣekúṣe, yóò sì fọgbọ́n yẹra fún ríré sínú wọn.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a Ọ̀rọ̀ náà “àjèjì” la lò fún àwọn tí kò rìn ní ìbámu pẹ̀lú Òfin mọ́, tí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ sọra wọn dọ̀tá Jèhófà. Nítorí náà, aṣẹ́wó náà—tó lè máà jẹ́ àjèjì ní ti gidi—la pè ní “àjèjì obìnrin.”
-