-
Kí Lèrò Tó Tọ́ Kéèyàn Ní Nípa Owó?Jí!—2007 | July
-
-
Ojú Ìwòye Bíbélì
Kí Lèrò Tó Tọ́ Kéèyàn Ní Nípa Owó?
BÍBÉLÌ sọ pé: ‘Ìdáàbòbò ni owó wà fún.’ (Oníwàásù 7:12) A lè sọ pé owó máa ń dáàbò boni lọ́wọ́ ìnira tí òṣì máa ń fà, torí pé bí ò bá sówó, a ò lè ra oúnjẹ àti aṣọ, a ò sì ní í ríbi gbé. Àní sẹ́, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ máà sí ohun tówó ò lè rà. Oníwàásù 10:19 tiẹ̀ sọ pé ó “ń mú ìdáhùn wá nínú ohun gbogbo.”
-
-
Kí Lèrò Tó Tọ́ Kéèyàn Ní Nípa Owó?Jí!—2007 | July
-
-
Ohun Tó Ju Owó Lọ
Nígbà tí Sólómọ́nì Ọba ń sọ pé owó lè jẹ́ ààbò, ó tún fi kún un pé, “ọgbọ́n jẹ́ fún ìdáàbòbò” nítorí pé ó “máa ń pa àwọn tí ó ni ín mọ́ láàyè.” (Oníwàásù 7:12) Kí ló ní lọ́kàn? Ọgbọ́n tí Sólómọ́nì ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ níbí yìí ni ọgbọ́n téèyàn ní nítorí pé ó lóye Ìwé Mímọ́ dunjú tó sì tún bẹ̀rù Ọlọ́run látọkànwá. Nítorí pé irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀ ju owó lọ fíìfíì, ó lè dáàbò bo èèyàn lọ́wọ́ àìmọye ọ̀fìn téèyàn lè kó sí láyé, kódà ó lè gbani lọ́wọ́ ikú àìtọ́jọ́ pàápàá. Ọgbọ́n tòótọ́ sì tún dà bí adé nítorí pé ó máa ń gbé àwọn tó bá ní in ga, ó sì tún máa ń jẹ́ káwọn èèyàn bọ̀wọ̀ fún wọn. (Òwe 2:10-22; 4:5-9) Nítorí pé irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀ sì máa ń mú kéèyàn rí ojú rere Ọlọ́run, Bíbélì tún pè é ní “igi ìyè.”—Òwe 3:18.
Gbogbo àwọn tó bá fi tọkàntọkàn fẹ́ irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀, tí wọ́n sì múra tán láti wá a rí, máa ń rí i pé ó wà lárọ̀ọ́wọ́tó. Ìyẹn ni Bíbélì fi sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ . . . bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an. Nítorí Jèhófà fúnra rẹ̀ ní ń fúnni ní ọgbọ́n; láti ẹnu rẹ̀ ni ìmọ̀ àti ìfòyemọ̀ ti ń wá.”—Òwe 2:1-6.
-