-
Jíjẹ́ Onídùnnú-ayọ̀ Nísinsìnyí àti Títí LáéIlé-Ìṣọ́nà—1996 | February 15
-
-
17, 18. Ní ọ̀nà wo ni paradise kan fi wà nísinsìnyí, kí sì ni ipa tí èyí ní lórí wa?
17 Nítorí náà, a lè wo Isaiah orí 35, kí a sì ní ìmúṣẹ lọ́ọ́lọ́ọ́ ti ẹsẹ 1 sí 8 lọ́kàn. Kò ha ṣe kedere pé, a ti rí ohun tí a fi ẹ̀tọ́ pè ní paradise tẹ̀mí bí? Rárá o, kò pé pérépéré—ó ṣì kù díẹ̀. Ṣùgbọ́n paradise ni ní tòótọ́, nítorí pé bí ẹsẹ 2 ti sọ, a lè “rí ògo Oluwa, àti ẹwà Ọlọrun wa” níhìn-ín nísinsìnyí. Kí sì ni àbájáde rẹ̀? Ẹsẹ 10 sọ pé: “Àwọn ẹni ìràpadà Oluwa yóò padà, wọn óò wá sí Sioni ti àwọn ti orin, ayọ̀ àìnípẹ̀kun yóò sì wà ní orí wọn: wọn óò rí ayọ̀ àti inú dídùn gbà, ìkáàánú òun ìmí-ẹ̀dùn yóò sì fò lọ.” Ní tòótọ́, jíjáde tí a jáde kúrò nínú ìsìn èké, tí a sì ń lépa ìjọsìn tòótọ́ lábẹ́ ojú rere Ọlọrun jẹ́ èyí tí ń mú ìdùnnú-ayọ̀ wá.
-
-
Jíjẹ́ Onídùnnú-ayọ̀ Nísinsìnyí àti Títí LáéIlé-Ìṣọ́nà—1996 | February 15
-
-
24. Èé ṣe tí o fi lè fohùn ṣọ̀kan pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí ó wà ní Isaiah 35:10?
24 Isaiah mú un dá wa lójú pé: “Àwọn ẹni ìràpadà Oluwa yóò padà, wọn óò wá sí Sioni ti àwọn ti orin, ayọ̀ àìnípẹ̀kun yóò sì wà ní orí wọn.” Nítorí náà, a lè fohùn ṣọ̀kan pé, a ní ìdí láti ké jáde fún ìdùnnú-ayọ̀. Ìdùnnú-ayọ̀ lórí ohun tí Jehofa ń ṣe nísinsìnyí fún àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú paradise tẹ̀mí tí ó jẹ́ tiwa, àti ìdùnnú-ayọ̀ lórí ohun tí a lè retí nínú Paradise gidi tí ó kù sí dẹ̀dẹ̀. Nípa àwọn onídùnnú-ayọ̀—nípa wa—Isaiah kọ̀wé pé: “Wọn óò rí ayọ̀ àti inú dídùn gbà, ìkáàánú òun ìmí-ẹ̀dùn yóò sì fò lọ.”—Isaiah 35:10.
-