-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 15
-
-
Bibeli sábà máa ń lo ohun ọ̀gbìn, bí igi kan, lọ́nà àpèjúwe. Nígbà mìíràn èyí máa ń jẹ́rìí sí òtítọ́ náà pé irúgbìn kan ń hù ó sì ń dàgbà, gbòǹgbò ń dàgbà ṣáájú ẹ̀ka-igi, àwọn ẹ̀ka mìíràn, tàbí èso níwọ̀n bí gbòǹgbò náà ti jẹ́ orísun gbogbo wọn. Fún àpẹẹrẹ, Isaiah 37:31 kà pé: “Àti ìyókù tí ó sálà nínú ilé Juda yóò tún fi gbòǹgbò múlẹ̀ nísàlẹ̀, yóò sì so èso lókè.”—Jobu 14:8, 9; Isaiah 14:29.
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 15
-
-
Èdè-ọ̀rọ̀ tí a lò ní Isaiah 37:31 àti Malaki 4:1 jẹ́rìí sí òtítọ́ náà pé àwọn ẹ̀ka (àti èso tí ó wà lára àwọn ọwọ́ ẹ̀ka) gba ìwàláàyè wọn láti ọ̀dọ̀ gbòǹgbò. Èyí ni kọ́kọ́rọ́ náà sí lílóye bí Jesu ṣe jẹ́ “kùkùté Jesse” àti “gbòǹgbò Dafidi.”
-