-
Àsọtẹ́lẹ̀ Ọ̀rọ̀ Ìtùnú Tí Ó Kàn Ọ́Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
6. Báwo ni wòlíì yìí ṣe ṣàpèjúwe aṣẹ́gun tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú?
6 Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀ nípa aṣẹ́gun kan tí yóò gba àwọn èèyàn Ọlọ́run là kúrò lọ́wọ́ Bábílónì, tí yóò sì dá àwọn ọ̀tá wọn lẹ́jọ́. Jèhófà béèrè pé: “Ta ni ó ti gbé ẹnì kan dìde láti yíyọ oòrùn? Ta ni ó tẹ̀ síwájú nínú òdodo láti pè é wá síbi ẹsẹ̀ Rẹ̀, láti fi àwọn orílẹ̀-èdè fún un níwájú rẹ̀, àti láti mú kí ó máa tẹ àwọn ọba pàápàá lórí ba nìṣó? Ta ni ó ń fi wọ́n fún un bí ekuru fún idà rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé a ń fi ọrun rẹ̀ gbá wọn kiri bí àgékù pòròpórò lásán-làsàn? Ta ni ó ń lépa wọn, tí ó ń fi ẹsẹ̀ rìn lọ ní àlàáfíà ní ipa ọ̀nà tí òun kò gbà wá? Ta ni ó ti ń gbé kánkán ṣiṣẹ́, tí ó sì ti ṣe èyí, tí ó ń pe àwọn ìran jáde láti ìbẹ̀rẹ̀? Èmi, Jèhófà ni, tí í ṣe Ẹni Àkọ́kọ́; àti pẹ̀lú àwọn ẹni ìkẹyìn, èmi kan náà ni.”—Aísáyà 41:2-4.
-
-
Àsọtẹ́lẹ̀ Ọ̀rọ̀ Ìtùnú Tí Ó Kàn Ọ́Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
8. Kí ni nǹkan náà tó jẹ́ pé Jèhófà nìkan ló lè ṣe é?
8 Nípa báyìí, Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìdìde Kírúsì tipẹ́tipẹ́ ṣáájú kí wọ́n tó bí ọba yẹn. Àfi Ọlọ́run tòótọ́ nìkan ló lè sọ àsọtẹ́lẹ̀ irú nǹkan bẹ́ẹ̀, tí kò sì ní yẹ̀. Kò sí ìkankan lára gbogbo òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tó bá Jèhófà dọ́gba. Ìdí rèé tí Jèhófà fi sọ pé: “Èmi kì yóò sì fi ògo mi fún ẹlòmíràn.” Jèhófà nìkan ló lẹ́tọ̀ọ́ láti sọ pé: “Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìkẹyìn, yàtọ̀ sí mi, kò sí Ọlọ́run kankan.”—Aísáyà 42:8; 44:6, 7.
-