-
Ta ni Yóò Ṣàkóso Ayé?Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
Kírúsì wá gbára dì láti lọ gbéjà ko ilẹ̀ Bábílónì alágbára ńlá. Láti orí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí síwájú ni ó sì ti di ọ̀kan nínú àwọn tí ń mú àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ṣẹ. Ní nǹkan bí ọ̀rúndún méjì ṣáájú, Jèhófà ti tipasẹ̀ wòlíì Aísáyà dárúkọ Kírúsì gẹ́gẹ́ bí alákòóso tí yóò gbàjọba mọ́ Bábílónì lọ́wọ́ tí yóò sì tú àwọn Júù sílẹ̀ nígbèkùn. Nítorí yíyàn tí a yàn án ṣáájú yìí ni Ìwé Mímọ́ fi tọ́ka sí Kírúsì gẹ́gẹ́ bí “ẹni àmì òróró” Jèhófà.—Aísáyà 44:26-28.
-
-
Ta ni Yóò Ṣàkóso Ayé?Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
Ní ti àwọn Júù tí ó wà ní Bábílónì, ṣíṣẹ́gun tí Kírúsì ṣẹ́gun yìí fi hàn pé ìdásílẹ̀ kúrò nígbèkùn tí wọ́n ti ń retí tipẹ́tipẹ́ ti dé, pé ìsọdahoro tí ó bá ìlú ìbílẹ̀ wọn láti àádọ́rin ọdún wá ti dópin. Ẹ wo bí inú wọn ṣe máa dùn tó nígbà tí Kírúsì gbé ìkéde jáde pé a fún wọn láṣẹ láti padà sí Jerúsálẹ́mù kí wọ́n sì tún tẹ́ńpìlì rẹ̀ kọ́! Kírúsì tún dá àwọn ohun èlò iyebíye inú tẹ́ńpìlì tí Nebukadinésárì kó wá sí Bábílónì padà fún wọn, ó sì fún wọn ní ìyọ̀ǹda láti ọ̀dọ̀ ọba pé kí wọ́n kó gẹdú wá láti Lẹ́bánónì, ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n fún wọn ní owó láti ilé ọba láti lè fi bójú tó ìnáwó iṣẹ́ ìkọ́lé náà.—Ẹ́sírà 1:1-11; 6:3-5.
-