ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọ̀rọ̀ Àgàn Náà Dayọ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • A Sọ Ẹni Tí “Obìnrin” Yẹn Jẹ́

      3. Kí ni ìdí tí àgàn yìí yóò fi dẹni tó ń yọ̀?

      3 Ọ̀rọ̀ ìdùnnú ni orí kẹrìnléláàádọ́ta fi bẹ̀rẹ̀, ó ní: “‘Fi ìdùnnú ké jáde, ìwọ àgàn tí kò bímọ! Fi igbe ìdùnnú tújú ká, kí o sì ké lọ́nà híhan gan-an-ran, ìwọ tí kò ní ìrora ìbímọ, nítorí àwọn ọmọ ẹni tí ó ti di ahoro pọ̀ níye ju àwọn ọmọ obìnrin tí ó ní ọkọ tí í ṣe olówó orí rẹ̀,’ ni Jèhófà wí.” (Aísáyà 54:1) Áà, yóò dùn mọ́ Aísáyà gan-an ni bó ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ yìí! Ìtùnú ńlá mà ni ìmúṣẹ rẹ̀ yóò sì jẹ́ fáwọn Júù tó wà nígbèkùn ní Bábílónì o! Ní àsìkò yẹn, ahoro ni Jerúsálẹ́mù yóò ṣì wà. Lójú ọmọ aráyé, yóò jọ pé kò sí ìrètí kankan pé àwọn èèyàn yóò tún padà máa gbébẹ̀, àní bí àgàn tó ti darúgbó kò ṣe ní retí pé òun yóò tún bímọ. Ṣùgbọ́n o, ìbùkún ńláǹlà ń bẹ fún “obìnrin” yìí lọ́jọ́ iwájú, ìyẹn ni pé, yóò di abiyamọ. Ayọ̀ Jerúsálẹ́mù á sì pọ̀ jọjọ. “Àwọn ọmọ” tàbí aráàlú yóò tún padà kún ibẹ̀ fọ́fọ́.

      4. (a) Báwo ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ṣe ràn wá lọ́wọ́ láti rí i pé Aísáyà orí kẹrìnléláàádọ́ta yóò ní láti ṣẹ lọ́nà kan tó ju èyí tó ṣẹ lọ́dún 537 ṣáájú Sànmánì Tiwa? (b) Kí ni “Jerúsálẹ́mù ti òkè”?

      4 Àsọtẹ́lẹ̀ tí Aísáyà sọ yìí yóò ṣẹ ju ẹ̀ẹ̀kan lọ, bó tilẹ̀ jẹ́ pé òun pàápàá lè má mọ̀ bẹ́ẹ̀. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fa ọ̀rọ̀ yọ látinú orí kẹrìnléláàádọ́ta ìwe Aísáyà, ó wá ṣàlàyé pé “obìnrin” yìí tọ́ka sí ohun tó túbọ̀ ṣe pàtàkì ju ìlú Jerúsálẹ́mù ti ilẹ̀ ayé lọ. Ó kọ̀wé pé: “Jerúsálẹ́mù ti òkè jẹ́ òmìnira, òun sì ni ìyá wa.” (Gálátíà 4:26) Kí ni “Jerúsálẹ́mù ti òkè” yìí? Ó dájú pé kì í ṣe ìlú Jerúsálẹ́mù tó wà ní Ilẹ̀ Ìlérí. Nítorí pé ayé yìí ni ìlú yẹn wà ní tiẹ̀, kì í ṣe “òkè” ọ̀run lọ́hùn-ún. “Jerúsálẹ́mù ti òkè” jẹ́ “obìnrin” Ọlọ́run tó wà ní ọ̀run, ìyẹn ètò àjọ àwọn ẹ̀dá ẹ̀mí alágbára tí Ọlọ́run ní.

      5. Nínú àwòkẹ́kọ̀ọ́ ìṣàpẹẹrẹ tó wà nínú Gálátíà 4:22-31, ta ló dúró fún (a) Ábúráhámù? (b) Sárà? (d) Ísákì? (e) Hágárì? (ẹ) Íṣímáẹ́lì?

      5 Àmọ́, báwo ni Jèhófà ṣe lè ní obìnrin ìṣàpẹẹrẹ méjì, kí ọ̀kan jẹ́ ti ọ̀run kí èkejì sì jẹ́ ti ayé? Ṣé ọ̀ràn ibí yìí kò ta kora báyìí? Rárá o. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi hàn pé inú ìdílé Ábúráhámù tó jẹ́ àpẹẹrẹ ohun tí àsọtẹ́lẹ̀ wí la ó ti rí ìdáhùn sí i. (Gálátíà 4:22-31; wo “Ìdílé Ábúráhámù—Àpẹẹrẹ Tó Jẹ́ Àsọtẹ́lẹ̀,” lójú ewé 218.) Sárà aya Ábúráhámù, tó jẹ́ “òmìnira obìnrin,” dúró fún ètò àjọ àwọn ẹ̀dá ẹ̀mí tó dà bí aya fún Jèhófà. Hágárì tó jẹ́ ìránṣẹ́bìnrin, tí í ṣe aya onípò kejì, tàbí wáhàrì Ábúráhámù, dúró fún Jerúsálẹ́mù ti ilẹ̀ ayé.

      6. Ọ̀nà wo ni ètò àjọ Ọlọ́run ní ọ̀run gbà yàgàn fún ọdún gbọ̀ọ̀rọ̀ gbọọrọ?

      6 Òye ìtàn àtẹ̀yìnwá yìí ń jẹ́ ká bẹ̀rẹ̀ sí rí bí Aísáyà 54:1 ti ṣe pàtàkì gidigidi tó. Lẹ́yìn tí Sárà ti yàgàn fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, ó padà wá bí Ísákì nígbà tó dẹni àádọ́rùn-ún ọdún. Lọ́nà kan náà, sáà gígùn gbọ̀ọ̀rọ̀ gbọọrọ ni ètò àjọ Jèhófà ní ọ̀run fi yàgàn. Édẹ́nì lọ́hùn-ún ni Jèhófà ti ṣèlérí pé “obìnrin” òun yóò bí “irú ọmọ” náà. (Jẹ́nẹ́sísì 3:15) Ní ohun tó ju ẹgbẹ̀rún ọdún méjì lẹ́yìn ìgbà yẹn, Jèhófà bá Ábúráhámù dá májẹ̀mú nípa Irú Ọmọ ìlérí yìí. Àmọ́ “obìnrin” Ọlọ́run ti ọ̀run yìí yóò ní láti dúró di ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rúndún sí i kí ó tó bí Irú Ọmọ yẹn. Síbẹ̀, àkókò dé tí àwọn ọmọ “àgàn” ìgbà kan rí yìí wá pọ̀ ju ti Ísírẹ́lì nípa ti ara lọ. Àkàwé àgàn yìí jẹ́ ká rí ìdí tí àwọn áńgẹ́lì fi ń hára gàgà láti rí i kí Irú Ọmọ tí àsọtẹ́lẹ̀ ń wí yìí dé. (1 Pétérù 1:12) Ìgbà wo ló sì wá dé níkẹyìn?

      7. Ìgbà wo ni àkókò ìdùnnú dé fún “Jerúsálẹ́mù ti òkè” gẹ́gẹ́ bí Aísáyà 54:1 ṣe wí, kí sì nìdí tóo fi dáhùn bẹ́ẹ̀?

      7 Dájúdájú, ìgbà ìbí Jésù gẹ́gẹ́ bí ọmọ èèyàn jẹ́ àkókò ìdùnnú fún àwọn áńgẹ́lì. (Lúùkù 2:9-14) Àmọ́, ìyẹn kọ́ ni ìṣẹ̀lẹ̀ tí Aísáyà 54:1 sọ tẹ́lẹ̀. Ìgbà tí ẹ̀mí mímọ́ bà lé Jésù lọ́dún 29 Sànmánì Tiwa ló tó ṣẹ̀ṣẹ̀ di ọmọ nípa tẹ̀mí fún “Jerúsálẹ́mù ti òkè,” tí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ sí sọ fáyé gbọ́ pé ó jẹ́ “Ọmọ” òun “olùfẹ́ ọ̀wọ́n.” (Máàkù 1:10, 11; Hébérù 1:5; 5:4, 5) Ìgbà yẹn ni “obìnrin” Ọlọ́run ní ọ̀run wá rí ìdí tó fi lè bú sí ayọ̀, ní ìmúṣẹ Aísáyà 54:1. Nígbẹ̀yìngbẹ́yín, ó bí Mèsáyà, Irú Ọmọ táa ṣèlérí náà! Ni ipò àgàn tó ti wà láti ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún bá dópin. Àmọ́ ṣá, ibẹ̀ yẹn nìkan kọ́ ni ìdùnnú rẹ̀ mọ.

      Àgàn Di Ọlọ́mọ Yọyọ

      8. Kí nìdí tí ìdùnnú fi lè bá “obìnrin” Ọlọ́run ní ọ̀run lẹ́yìn tó bí Irú Ọmọ táa ṣèlérí náà?

      8 Ìdùnnú bá “obìnrin” Ọlọ́run tó wà ní ọ̀run yìí lẹ́yìn tí Jésù kú tó sì tún jíǹde, nítorí pé ó rí ààyò Ọmọ yìí gbà padà gẹ́gẹ́ bí “àkọ́bí láti inú òkú.” (Kólósè 1:18) Ẹ̀yìn ìyẹn ló wá bẹ̀rẹ̀ sí bí àwọn ọmọ tẹ̀mí púpọ̀ sí i. Ní Pẹ́ńtíkọ́sì ọdún 33 Sànmánì Tiwa, nǹkan bí ọgọ́fà ọmọlẹ́yìn Jésù la fi ẹ̀mí mímọ́ yàn, tí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ di àjùmọ̀jogún pẹ̀lú Kristi. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ sí i lọ́jọ́ tí à ń wí yìí, ẹgbẹ̀ẹ́dógún [3,000 ] èèyàn tún kún wọn. (Jòhánù 1:12; Ìṣe 1:13-15; 2:1-4, 41; Róòmù 8:14-16) Ló bá di pé àwùjọ àwọn ọmọ yìí bẹ̀rẹ̀ sí pọ̀ sí i. Àmọ́ ṣá, ní àwọn ọ̀rúndún tó wà lápá ìbẹ̀rẹ̀ ìpẹ̀yìndà Kirisẹ́ńdọ̀mù, ení tere èjì tere ni wọ́n ń wá. Ṣùgbọ́n nígbà tó di ọ̀rúndún ogún, ìyẹn yí padà.

  • Ọ̀rọ̀ Àgàn Náà Dayọ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 220]

      Lẹ́yìn tí Jésù ṣèrìbọmi, Jèhófà fẹ̀mí mímọ́ yàn án, Aísáyà 54:1 sì wà bẹ̀rẹ̀ sí ní ìmúṣẹ tó ṣe pàtàkì jù lọ

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́