ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ Jí
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • ‘Àlàáfíà fún Àwọn Tó Jìnnà àti Àwọn Tó Wà Nítòsí’

      22. Kí ni Jèhófà sọ tẹ́lẹ̀ pé ó ń bẹ níwájú fún (a) àwọn tó ronú pìwà dà? (b) àwọn ẹni ibi?

      22 Jèhófà wá ń fi ìyàtọ̀ hàn nípa ohun tí ń bẹ níwájú fún àwọn tó ronú pìwà dà àti fún àwọn tó ń bá àwọn ọ̀nà burúkú wọn lọ, ó ní: “Èmi yóò dá èso ètè. Àlàáfíà tí ń bá a lọ ni yóò wà fún ẹni tí ó jìnnà réré àti fún ẹni tí ó wà nítòsí, . . . èmi yóò sì mú un lára dá dájúdájú. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni burúkú dà bí òkun tí a ń bì síwá bì sẹ́yìn, nígbà tí kò lè rọ̀ wọ̀ọ̀, èyí tí omi rẹ̀ ń sọ èpò òkun àti ẹrẹ̀ sókè. Àlàáfíà kò sí fún àwọn ẹni burúkú.”—Aísáyà 57:19-21.

  • Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ Jí
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 23. Kí ni èso ètè, ọ̀nà wo sì ni Jèhófà gbà “dá” èso ètè yìí?

      23 Èso ètè ni ẹbọ ìyìn tí a ń rú sí Ọlọ́run, ìyẹn pípolongo orúkọ rẹ̀ ní gbangba. (Hébérù 13:15) Báwo ni Jèhófà ṣe ń “dá” ìpolongo ní gbangba yẹn? Láti lè rú ẹbọ ìyìn, èèyàn ní láti kọ́kọ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ọlọ́run kí ó sì gbà á gbọ́. Ìgbàgbọ́ tí í ṣe ara èso ẹ̀mí Ọlọ́run ni yóò wá sún onítọ̀hún láti máa sọ ohun tí ó gbọ́ fún àwọn ẹlòmíràn. Ó ń polongo ní gbangba nìyẹn. (Róòmù 10:13-15; Gálátíà 5:22) Kí á sì tún rántí pé Jèhófà gan-an ló yan iṣẹ́ fáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n lọ máa kéde ìyìn òun. Jèhófà sì ni ó dá àwọn èèyàn rẹ̀ nídè, èyí tó mú kó ṣeé ṣe fún wọn láti lè rú irú ẹbọ ìyìn yẹn. (1 Pétérù 2:9) Nípa bẹ́ẹ̀, a lè sọ ọ́ dájúdájú pé Jèhófà ló dá èso ètè yìí.

      24. (a) Àwọn wo ló wá mọ àlàáfíà Ọlọ́run, kí sì ni àbáyọrí rẹ̀? (b) Ta ni kò wá mọ àlàáfíà rárá, kí sì ni àbáyọrí rẹ̀ fún wọn?

      24 Ẹbọ èso ètè tí àwọn Júù sì rú nígbà tí wọ́n padà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn ti àwọn ti orin ìyìn sí Jèhófà á mà sì pọ̀ gan-an o! Wọn ì báà wà níbi tó “jìnnà réré,” ìyẹn ọ̀nà jíjìn sí Júdà, kí wọ́n máa dúró de ìgbà tí wọn yóò padà sílé, tàbí kí wọ́n wà “nítòsí,” ìyẹn ni pé kí wọ́n ti wà nínú ìlú ìbílẹ̀ wọn, ìdùnnú ńlá ni yóò jẹ́ fún wọn láti mọ bí àlàáfíà Ọlọ́run ṣe máa ń rí. Ipò àwọn ẹni burúkú yàtọ̀ pátápátá gbáà sí tiwọn! Ẹnikẹ́ni tó bá kùnà láti kọbi ara sí ìyà ẹ̀ṣẹ̀ tí Jèhófà fi bá wọn wí, ìyẹn àwọn ẹni burúkú, àní ẹni yòówù kí wọ́n jẹ́ àti ibikíbi tí wọn ì báà wà, kò lè sí àlàáfíà fún wọn rárá. Nítorí ńṣe ni wọ́n ń ru gùdù bí òkun tí kò lè rọ̀ wọ̀ọ̀, èkìdá “èpò òkun àti ẹrẹ̀” tó jẹ́ ohun àìmọ́ gbogbo, ni wọ́n ń mú jáde ṣáá, wọn kò mú èso ètè jáde rárá.

  • Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ Jí
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 25. Báwo ni ọ̀pọ̀ èèyàn tó wà lọ́nà jíjìn àti nítòsí ṣe ń di ẹni tó mọ àlàáfíà?

      25 Lónìí pẹ̀lú, àwọn olùjọsìn Jèhófà níbi gbogbo ń kéde ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Àwọn Kristẹni tó wà lọ́nà jíjìn àti àwọn tó wà nítòsí, ní orílẹ̀-èdè tó ju igba ó lé ọgbọ̀n lọ, ń rú ẹbọ èso ètè wọn, tí wọ́n sì ń kókìkí ìyìn Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà. “Láti ìkángun ilẹ̀ ayé” pàápàá ni àwọn èèyàn ti ń gbóhùn orin ìyìn tí wọ́n ń kọ. (Aísáyà 42:10-12) Àwọn tó ń gbọ́ ohun tí wọ́n ń wí tí wọ́n sì kọbi ara sí i ń tẹ́wọ́ gba òtítọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí í ṣe Bíbélì. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ wá ń mọ àlàáfíà, èyí tí wọ́n ń rí látinú sísìn tí wọ́n ń sin “Ọlọ́run tí ń fúnni ní àlàáfíà.”—Róòmù 16:20.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́