-
Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ JíÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
22. Kí ni Jèhófà sọ tẹ́lẹ̀ pé ó ń bẹ níwájú fún (a) àwọn tó ronú pìwà dà? (b) àwọn ẹni ibi?
22 Jèhófà wá ń fi ìyàtọ̀ hàn nípa ohun tí ń bẹ níwájú fún àwọn tó ronú pìwà dà àti fún àwọn tó ń bá àwọn ọ̀nà burúkú wọn lọ, ó ní: “Èmi yóò dá èso ètè. Àlàáfíà tí ń bá a lọ ni yóò wà fún ẹni tí ó jìnnà réré àti fún ẹni tí ó wà nítòsí, . . . èmi yóò sì mú un lára dá dájúdájú. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni burúkú dà bí òkun tí a ń bì síwá bì sẹ́yìn, nígbà tí kò lè rọ̀ wọ̀ọ̀, èyí tí omi rẹ̀ ń sọ èpò òkun àti ẹrẹ̀ sókè. Àlàáfíà kò sí fún àwọn ẹni burúkú.”—Aísáyà 57:19-21.
-
-
Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ JíÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
24. (a) Àwọn wo ló wá mọ àlàáfíà Ọlọ́run, kí sì ni àbáyọrí rẹ̀? (b) Ta ni kò wá mọ àlàáfíà rárá, kí sì ni àbáyọrí rẹ̀ fún wọn?
24 Ẹbọ èso ètè tí àwọn Júù sì rú nígbà tí wọ́n padà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn ti àwọn ti orin ìyìn sí Jèhófà á mà sì pọ̀ gan-an o! Wọn ì báà wà níbi tó “jìnnà réré,” ìyẹn ọ̀nà jíjìn sí Júdà, kí wọ́n máa dúró de ìgbà tí wọn yóò padà sílé, tàbí kí wọ́n wà “nítòsí,” ìyẹn ni pé kí wọ́n ti wà nínú ìlú ìbílẹ̀ wọn, ìdùnnú ńlá ni yóò jẹ́ fún wọn láti mọ bí àlàáfíà Ọlọ́run ṣe máa ń rí. Ipò àwọn ẹni burúkú yàtọ̀ pátápátá gbáà sí tiwọn! Ẹnikẹ́ni tó bá kùnà láti kọbi ara sí ìyà ẹ̀ṣẹ̀ tí Jèhófà fi bá wọn wí, ìyẹn àwọn ẹni burúkú, àní ẹni yòówù kí wọ́n jẹ́ àti ibikíbi tí wọn ì báà wà, kò lè sí àlàáfíà fún wọn rárá. Nítorí ńṣe ni wọ́n ń ru gùdù bí òkun tí kò lè rọ̀ wọ̀ọ̀, èkìdá “èpò òkun àti ẹrẹ̀” tó jẹ́ ohun àìmọ́ gbogbo, ni wọ́n ń mú jáde ṣáá, wọn kò mú èso ètè jáde rárá.
-