-
“Orúkọ Tuntun” KanÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
‘Jèhófà Ní Inú Dídùn sí Ọ’
9. Ṣàpèjúwe àyípadà tó bá Síónì.
9 Orúkọ tuntun tí Síónì ti ọ̀run wá ń jẹ́ ni ara àyípadà dídùnmọ́ni tó dé bá a, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe hàn látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ rẹ̀ orí ilẹ̀ ayé. A kà á pé: “A kì yóò sọ mọ́ pé ìwọ jẹ́ obìnrin tí a fi sílẹ̀ pátápátá; a kì yóò sì sọ mọ́ pé ilẹ̀ rẹ wà ní ahoro; ṣùgbọ́n a óò máa pe ìwọ alára ní Inú Dídùn Mi Wà Nínú Rẹ̀, a ó sì máa pe ilẹ̀ rẹ ní Èyí Tí A Mú Ṣe Aya. Nítorí pé Jèhófà yóò ti ní inú dídùn sí ọ, ilẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ èyí tí a mú ṣe aya.” (Aísáyà 62:4) Láti ọdún 607 ṣááju Sànmánì Tiwa ni Síónì orí ilẹ̀ ayé ti wà láhoro. Àmọ́, ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ yìí fi í lọ́kàn balẹ̀ pé yóò padà bọ̀ sípò àti pé àwọn èèyàn yóò padà máa wá gbé inú ilẹ̀ rẹ̀. Síónì tó ti fìgbà kan wà láhoro kò ní jẹ́ obìnrin tí a fi sílẹ̀ pátápátá mọ́, ilẹ̀ rẹ̀ kò sì ní wà láhoro mọ́. Ipò tuntun ni pípadà tí Jerúsálẹ́mù padà bọ̀ sípò lọ́dún 537 ṣááju Sànmánì Tiwa jẹ́ fún un, ó yàtọ̀ pátápátá sí ahoro tó ti wà látẹ̀yìnwá. Jèhófà kéde pé, a óò máa pe Síónì ní “Inú Dídùn Mi Wà Nínú Rẹ,” àti ilẹ̀ rẹ̀ ní “Èyí Tí A Mú Ṣe Aya.”—Aísáyà 54:1, 5, 6; 66:8; Jeremáyà 23:5-8; 30:17; Gálátíà 4:27-31.
10. (a) Báwo ni àyípadà ṣe bá Ísírẹ́lì Ọlọ́run? (b) Kí ni “ilẹ̀” Ísírẹ́lì Ọlọ́run?
10 Ọdún 1919 ni irú àyípadà bẹ́ẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí bá Ísírẹ́lì Ọlọ́run. Nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, ńṣe ló dà bíi pé Ọlọ́run kọ àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró sílẹ̀. Àmọ́ lọ́dún 1919, wọ́n tún padà sí ipò ojú rere tí wọ́n wà tẹ́lẹ̀, ọ̀nà tí wọ́n gbà ń jọ́sìn sì di èyí táa yọ́ mọ́. Èyí kan àwọn ẹ̀kọ́ tí wọ́n fi ń kọ́ni, ó kan ètò àjọ wọn, ó sì kan ìgbòkègbodò wọn. Ni Ísírẹ́lì Ọlọ́run wá dẹni tó wá sí “ilẹ̀” rẹ̀, ìyẹn ipò rẹ̀ tàbí àgbègbè ìgbòkègbodò rẹ̀ nípa tẹ̀mí.—Aísáyà 66:7, 8, 20-22.
-
-
“Orúkọ Tuntun” KanÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 339]
Jèhófà yóò sọ Síónì ti ọ̀run ní orúkọ tuntun kan
-