ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìgbàlà àti Ayọ̀ Lábẹ́ Àkóso Mèsáyà
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • 6. Irú alákòóso wo ni àsọtẹ́lẹ̀ sọ pé Mèsáyà yóò jẹ́?

      6 Irú alákòóso wo ni Mèsáyà yóò jẹ́? Ṣé yóò ya òṣìkà, aṣetinú-ẹni bíi ará Ásíríà tó pa ìjọba Ísírẹ́lì tó jẹ́ ẹ̀yà mẹ́wàá níhà àríwá run ni? Rárá o. Aísáyà sọ nípa Mèsáyà pé: “Ẹ̀mí Jèhófà yóò sì bà lé e, ẹ̀mí ọgbọ́n àti ti òye, ẹ̀mí ìmọ̀ràn àti ti agbára ńlá, ẹ̀mí ìmọ̀ àti ti ìbẹ̀rù Jèhófà; ìgbádùn rẹ̀ yóò sì wà nínú ìbẹ̀rù Jèhófà.” (Aísáyà 11:2, 3a) Òróró kọ́ ni wọ́n fi yan Mèsáyà, ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ni. Èyí wáyé nígbà tí Jésù ṣe batisí, tí Jòhánù Olùbatisí rí i tí ẹ̀mí Ọlọ́run sọ̀ kalẹ̀ bí àdàbà sórí Jésù. (Lúùkù 3:22) Ẹ̀mí Jèhófà “bà lé” Jésù, ó sì fi ẹ̀rí èyí hàn nínú bó ṣe ń fi ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ràn, agbára ńlá, àti ìmọ̀ ṣe àwọn nǹkan. Àwọn àgbàyanu ànímọ́ tó yẹ alákòóso gan-an nìwọ̀nyí!

  • Ìgbàlà àti Ayọ̀ Lábẹ́ Àkóso Mèsáyà
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • 8. Báwo ni Jésù ṣe rí ìgbádùn nínú ìbẹ̀rù Jèhófà?

      8 Kí ni ìbẹ̀rù Jèhófà tí Mèsáyà ní? Ó dájú pé Ọlọ́run kò da jìnnìjìnnì bo Jésù, kó wá di pé ẹ̀rù ìbáwí rẹ̀ ló ń bà á. Kàkà bẹ́ẹ̀, tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni Mèsáyà fi bẹ̀rù Ọlọ́run, ó fi ìfẹ́ bọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ fún un. Olùbẹ̀rù Ọlọ́run a máa fẹ́ láti “ṣe ohun tí ó wù ú” ní gbogbo ìgbà, bí Jésù ti ṣe. (Jòhánù 8:29) Nínú ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe, Jésù kọ́ni pé kò sóhun tó ń múni láyọ̀ bíi pé kéèyàn máa fi ojúlówó ìbẹ̀rù Jèhófà gbé ìgbésí ayé rẹ̀ ojoojúmọ́.

      Onídàájọ́ Òdodo àti Aláàánú

      9. Àpẹẹrẹ wo ni Jésù fi lélẹ̀ fún àwọn táa bá ní kí wọ́n bójú tó ọ̀ràn ìdájọ́ nínú ìjọ Kristẹni?

      9 Aísáyà túbọ̀ sọ tẹ́lẹ̀ nípa àwọn ànímọ́ Mèsáyà pé: “Kì yóò . . . ṣe ìdájọ́ nípasẹ̀ ohun èyíkéyìí tí ó hàn lásán sí ojú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi ìbáwí tọ́ni sọ́nà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí etí rẹ̀ wulẹ̀ gbọ́.” (Aísáyà 11:3b) Ká ní o fẹ́ rojọ́ ní kóòtù, inú rẹ kò ha ní dùn tóo bá rí irú adájọ́ yìí? Bí Mèsáyà ṣe jẹ́ Onídàájọ́ gbogbo aráyé, rírojọ́ èké, lílo ọgbọ́n àyínìke ní kóòtù, àgbọ́sọ, tàbí àwọn ohun mìíràn tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀, bíi jíjẹ́ ọlọ́rọ̀, kò lè nípa lórí rẹ̀. Ó rí àṣírí gbogbo ẹ̀tàn, ó ń wò ré kọjá ìrí ojú lásán, ó sì ń fòye mọ “ẹni ìkọ̀kọ̀ ti ọkàn-àyà,” “ọkùnrin tó fara sin.” (1 Pétérù 3:4, àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé, NW) Àpẹẹrẹ títayọ tí Jésù fi lélẹ̀ jẹ́ àwòkọ́ṣe fún gbogbo àwọn táa bá ní kí wọ́n bójú tó ọ̀ràn ìdájọ́ nínú ìjọ Kristẹni.—1 Kọ́ríńtì 6:1-4.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́