-
“Bábílónì Ti Ṣubú!”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
8. Bí àsọtẹ́lẹ̀ ṣe fi hàn, kí ni àwọn ará Bábílónì ń ṣe, bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọ̀tá wọn wà lẹ́yìn odi wọn?
8 Kò sóhun tó jẹ mọ́ jìnnìjìnnì lọ́kàn àwọn ará Bábílónì rárá bí ilẹ̀ ọjọ́ burúkú yẹn ṣe ń ṣú lọ. Ní nǹkan bí ọ̀rúndún méjì ṣáájú ni Aísáyà ti sọ tẹ́lẹ̀ pé: “Kí títẹ́ tábìlì, ṣíṣètò àyè ìjókòó, jíjẹ, mímu ṣẹlẹ̀!” (Aísáyà 21:5a) Bẹ́ẹ̀ ni, àsè rẹpẹtẹ ń lọ lọ́wọ́ lọ́dọ̀ Bẹliṣásárì Ọba agbéraga yẹn. Ẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn rẹ̀ jàǹkàn-jàǹkàn ló ṣètò àyè ìjókòó fún, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aya àti wáhàrì rẹ̀. (Dáníẹ́lì 5:1, 2) Àwọn tó ń ṣàríyá aláriwo yìí sì mọ̀ pé ẹgbẹ́ ọmọ ogun kan ń bẹ lẹ́yìn odi àwọn o, ṣùgbọ́n, wọ́n gbà gbọ́ pé mìmì kan ò lè mi ìlú àwọn. Àwọn odi rẹ̀ kìǹbà kìǹbà àtàwọn òjìngbùn-jingbùn yàrà rẹ̀ dà bí èyí tí kò lè jẹ́ kí wọ́n ṣẹ́gun ìlú yẹn láéláé; kò tiẹ̀ ṣeé ronú kàn ni lójú àwọn òrìṣà rẹpẹtẹ tó wà níbẹ̀. Nítorí náà, kí “jíjẹ, mímu” máa lọ ní rabidun o jàre! Ni Bẹliṣásárì bá mutí yó, kò sì lè jẹ́ pé òun nìkan ló ti yó. Láti mọ bí àwọn onípò àṣẹ gíga-gíga wọ̀nyẹn ṣe yó bìnàkò tó, ńṣe ni wọ́n ní láti máa ta wọ́n jí bí ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ tí Aísáyà sọ tẹ̀ lé e ṣe fi hàn.
9. Kí ló mú kó di dandan fún wọ́n láti “fòróró yan apata”?
9 Ó ní: “Ẹ dìde, ẹ̀yin ọmọ aládé, ẹ fòróró yan apata.” (Aísáyà 21:5b) Àsè yẹn dópin lójijì. Ńṣe làwọn ọmọ aládé ní láti gbọnra nù! Wọ́n ti pe wòlíì Dáníẹ́lì arúgbó wá síbẹ̀, ó sì rí bí Jèhófà ṣe da jìnnìjìnnì bo Bẹliṣásárì ọba Bábílónì lọ́nà tó jọ èyí tí Aísáyà ṣàpèjúwe rẹ̀. Ṣìbáṣìbo bá àwọn ènìyàn jàǹkàn-jàǹkàn ọba bí àpapọ̀ agbo ọmọ ogun àwọn ará Mídíà, Páṣíà àtàwọn ará Élámù ṣe fọ́ ètò ààbò ìlú yẹn. Kíá Bábílónì ti ṣubú! Ṣùgbọ́n, kí ni ìtumọ̀ “fòróró yan apata”? Nígbà mìíràn, Bíbélì máa ń pe ọba orílẹ̀-èdè kan ní apata orílẹ̀-èdè yẹn nítorí pé òun ló ń gbà á sílẹ̀ tó sì ń dáàbò bò ó.b (Sáàmù 89:18) Nítorí náà, ó jọ pé ẹsẹ Aísáyà yìí ń sọ tẹ́lẹ̀ pé wọ́n máa nílò ọba tuntun. Èé ṣe? Nítorí pé “òru ọjọ́ yẹn gan-an” ni wọ́n pa Bẹliṣásárì. Nípa bẹ́ẹ̀, ó di dandan pé kí wọ́n “fòróró yan apata,” tàbí kí wọ́n yan ọba tuntun.—Dáníẹ́lì 5:1-9, 30.
-
-
“Bábílónì Ti Ṣubú!”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
b Ọ̀pọ̀ àwọn alálàyé Bíbélì rò pé ọ̀rọ̀ náà, “fòróró yan apata,” ń tọ́ka sí ìṣe àwọn ológun ayé àtijọ́, tí wọ́n máa ń fi epo pa apata aláwọ ṣáájú ìjà, kí gbogbo ohun tó bá bà á lè máa yọ́ bọ́rọ́. Lóòótọ́, èyí lè jẹ́ ọ̀nà ìtumọ̀ kan, ṣùgbọ́n, ká ṣàkíyèsí pé, lóru ọjọ́ tí ìlú yẹn ṣubú, agbára káká làwọn ará Bábílónì fi ráyè jà, áńbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n á ráyè fi epo pa apata wọn ṣáájú ìjà!
-