-
Ẹ̀kọ́ Àríkọ́gbọ́n Nípa Ìwà Àìṣòótọ́Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
19, 20. (a) Báwo ni Élíákímù yóò ṣe jẹ́ ìbùkún fáwọn èèyàn rẹ̀? (b) Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn tó bá ṣì ń gbójú lé Ṣébínà?
19 Níkẹyìn, Jèhófà lo èdè àpèjúwe láti ṣàlàyé bí agbára yóò ṣe ti ọwọ́ Ṣébínà bọ́ sọ́wọ́ Élíákímù. Ó sọ pé: “‘Èmi yóò sì gbá a [Élíákímù] wọlé gẹ́gẹ́ bí èèkàn sí ibi wíwà pẹ́ títí, yóò sì dà bí ìtẹ́ ògo fún ilé baba rẹ̀. Wọn yóò sì gbé gbogbo ògo ilé baba rẹ̀ kọ́ sára rẹ̀, àwọn ọmọ ìran àti èéhù, gbogbo ohun èlò irú èyí tí ó kéré, àwọn ohun èlò irú èyí tí ó jẹ́ àwokòtò àti gbogbo ohun èlò tí ó jẹ́ àwọn ìṣà títóbi. Ní ọjọ́ yẹn,’ ni àsọjáde Jèhófà àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun, ‘èèkàn [Ṣébínà] tí a gbá wọ ibi wíwà pẹ́ títí ni a óò mú kúrò, a ó sì gbẹ́ ẹ kanlẹ̀, yóò sì ṣubú, ẹrù tí ó wà lára rẹ̀ sì ni a óò ké kúrò, nítorí pé Jèhófà tìkára rẹ̀ ti sọ ọ́.’”—Aísáyà 22:23-25.
20 Élíákímù ni èèkàn àkọ́kọ́ nínú ẹsẹ wọ̀nyí. Ńṣe ni yóò di “ìtẹ́ ògo” fún ilé Hilikáyà, baba rẹ̀. Kò ní ṣe bíi Ṣébínà, ní ti pé kò ní dójú ti ilé baba rẹ̀, kò sì ní borúkọ bàbá rẹ̀ jẹ́. Élíákímù yóò wá di èèkàn wíwà pẹ́ títí fáwọn ohun èlò ilé, ìyẹn àwọn yòókù tó wà lẹ́nu iṣẹ́ ọba. (2 Tímótì 2:20, 21) Ní ìdàkejì, Ṣébínà ni èèkàn kejì ń tọ́ka sí. Ó lè jọ bíi pé mìmì kan ò lè mì í, àmọ́ yíyọ ni wọ́n máa yọ ọ́. Ẹnikẹ́ni tó bá ṣì ń gbójú lé e yóò já bọ́.
-
-
Ẹ̀kọ́ Àríkọ́gbọ́n Nípa Ìwà Àìṣòótọ́Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 239]
Hesekáyà sọ Élíákímù di “èèkàn tí a gbá wọ ibi wíwà pẹ́ títí”
-