-
Jèhófà JọbaÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
6. Èé ṣe tí Jèhófà fi fawọ́ ìbùkún rẹ̀ sẹ́yìn lórí ilẹ̀ náà?
6 Kí àṣìlóye kankan má baà sí, Aísáyà ṣàpèjúwe bí ìjábá tó ń bọ̀ yìí ṣe máa jẹ́ ọ̀gbálẹ̀gbáràwé tó, ó sì ṣàlàyé ìdí rẹ̀, ó ní: “Ilẹ̀ náà ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣọ̀fọ̀, ó ti ṣá. Ilẹ̀ eléso ti gbẹ, ó ti ṣá. Àwọn ẹni gíga lára àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ti gbẹ. A ti sọ ilẹ̀ náà gan-an di eléèérí lábẹ́ àwọn olùgbé rẹ̀, nítorí pé wọ́n ti pẹ́ òfin kọjá, wọ́n ti yí ìlànà padà, wọ́n ti da májẹ̀mú tí ó wà fún àkókò tí ó lọ kánrin. Ìdí nìyẹn tí ègún pàápàá fi jẹ ilẹ̀ náà run, tí a sì ka àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ sí ẹlẹ́bi. Ìdí nìyẹn tí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà fi pẹ̀dín ní iye, tí ìwọ̀nba kéréje ẹni kíkú sì fi ṣẹ́ kù.” (Aísáyà 24:4-6) Nígbà tí wọ́n fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilẹ̀ Kénáánì, wọ́n bá a pé ó jẹ́ “ilẹ̀ kan tí ń ṣàn fún wàrà àti fún oyin.” (Diutarónómì 27:3) Síbẹ̀síbẹ̀, ìbùkún Jèhófà ni wọ́n gbára lé. Bí wọ́n bá fi ìṣòtítọ́ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́, ilẹ̀ náà ‘yóò fi èso rẹ̀ fúnni,’ ṣùgbọ́n tí wọ́n bá pẹ́ àwọn òfin àti àṣẹ rẹ̀ kọjá, ńṣe ni wọn yóò kàn máa “lo agbára [wọn] lásán” lẹ́nu iṣẹ́ oko wọn, ilẹ̀ ‘kì yóò mú èso rẹ̀ jáde.’ (Léfítíkù 26:3-5, 14, 15, 20) Ègún Jèhófà ni yóò ‘jẹ ilẹ̀ náà tán.’ (Diutarónómì 28:15-20, 38-42, 62, 63) Wàyí o, kí Júdà máa retí kí ègún yẹn ṣẹ lé òun lórí ló kù.
-
-
Jèhófà JọbaÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
8. (a) Báwo làwọn èèyàn yìí ṣe “pẹ́ òfin kọjá,” tí wọ́n sì “yí ìlànà padà”? (b) Àwọn ọ̀nà wo ló fi máa jẹ́ pé “àwọn ẹni gíga,” ló máa kọ́kọ́ “gbẹ”?
8 Àmọ́, ńṣe làwọn èèyàn yìí “da májẹ̀mú tí ó wà fún àkókò tí ó lọ kánrin.” Wọ́n pẹ́ àwọn òfin tí Ọlọ́run fún wọn kọjá, wọn ò sì kà wọ́n sí. Wọ́n “yí ìlànà padà,” wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí lo àwọn òfin mìíràn tó yàtọ̀ sí èyí tí Jèhófà fún wọn. (Ẹ́kísódù 22:25; Ìsíkíẹ́lì 22:12) Nítorí náà, kíkó ni wọ́n máa kó àwọn èèyàn náà kúrò ní ilẹ̀ náà. Kò sójú àánú kankan nígbà ìdájọ́ tó ń bọ̀ yìí. Lára àwọn ẹni tó máa kọ́kọ́ “gbẹ” nítorí bí Jèhófà ṣe fawọ́ ààbò àti ojú rere rẹ̀ sẹ́yìn lọ́dọ̀ wọn ni “àwọn ẹni gíga,” ìyẹn àwọn ọ̀tọ̀kùlú. Èyí ṣẹ ní ti pé, bí ìparun Jerúsálẹ́mù ṣe ń sún mọ́lé, àwọn ará Íjíbítì ló kọ́kọ́ sọ àwọn ọba Júdà di baálẹ̀ abẹ́ àkóso wọn, ẹ̀yìn ìyẹn ni wọ́n tún di baálẹ̀ lábẹ́ àwọn ará Bábílónì. Lẹ́yìn náà, Jèhóákínì Ọba àti àwọn ará ilé ọba wà lára àwọn tí wọ́n kọ́kọ́ kó lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì.—2 Kíróníkà 36:4, 9, 10.
-