-
“Nísinsìnyí Ẹ Jẹ́ Ènìyàn Ọlọ́run”Ilé Ìṣọ́—2014 | November 15
-
-
17, 18. (a) Ìtọ́ni wo làwọn èèyàn Jèhófà máa gbà nígbà tí Gọ́ọ̀gù bá kọ lù wọ́n? (b) Tá a bá fẹ́ kí Jèhófà dáàbò bò wá, kí la gbọ́dọ̀ ṣe?
17 Nígbà tí Gọ́ọ̀gù bá bẹ̀rẹ̀ ìkọlù rẹ̀, Jèhófà máa sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Lọ, ènìyàn mi, wọnú yàrá rẹ ti inú lọ́hùn-ún, kí o sì ti ilẹ̀kùn rẹ mọ́ ara rẹ. Fi ara rẹ pa mọ́ fún kìkì ìṣẹ́jú kan títí ìdálẹ́bi yóò fi ré kọjá.” (Aísá. 26:20) Ní irú àsìkò pàtàkì yẹn, Jèhófà máa fún wa láwọn ìtọ́ni tó ń gbẹ̀mí là, ó sì ṣeé kí ‘yàrá ti inú lọ́hùn-ún’ jẹ mọ́ àwọn ìjọ tá à ń dara pọ̀ mọ́.
18 Torí náà, tá a bá fẹ́ wà lábẹ́ ààbò tí Jèhófà máa pèsè nígbà ìpọ́njú ńlá, a gbọ́dọ̀ mọ̀ pé Jèhófà ní àwọn èèyàn lórí ilẹ̀ ayé, ìyẹn àwọn èèyàn tó ṣètò ní ìjọ-ìjọ. A gbọ́dọ̀ máa wà pẹ̀lú àwọn èèyàn Jèhófà nìṣó, ká sì rí i pé à ń dara pọ̀ mọ́ ìjọ tá a wà déédéé. Nítorí náà, ẹ jẹ́ ká fi gbogbo ọkàn wa sọ bí onísáàmù náà ti sọ pé: “Ìgbàlà jẹ́ ti Jèhófà. Ìbùkún rẹ wà lára àwọn ènìyàn rẹ.”—Sm. 3:8.
-