-
Ẹ Máa Bá A Lọ Láti Fojú Sọ́nà fún JèhófàÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
5, 6. (a) Èé ṣe tó fi jẹ́ pé àṣìṣe eléwu gbáà ni wọ́n ṣe láti lọ bá Íjíbítì mulẹ̀? (b) Ìrìn àjò wo ni àwọn èèyàn Ọlọ́run rìn níṣàájú tó jẹ́ kó hàn kedere pé ìwà òmùgọ̀ gidi ni gbígbéra tí wọ́n gbéra lọ sí Íjíbítì lọ́tẹ̀ yìí?
5 Aísáyà wá ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé síwájú sí i bí ẹni pé ó ń fi ìyẹn fèsì àwíjàre tí wọ́n lè fẹ́ wí, pé àwọn ońṣẹ́ tó lọ sí Íjíbítì kàn lọ ṣèbẹ̀wò lásán ni. Ó ní: “Ọ̀rọ̀ ìkéde lòdì sí àwọn ẹranko gúúsù: La ilẹ̀ wàhálà àti àwọn ipò ìnira kọjá, ti kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn tí ń kùn hùn-ùn, ti paramọ́lẹ̀ àti ejò oníná tí ń fò, èjìká àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ti dàgbà tán ni wọ́n fi ru àwọn ohun àmúṣọrọ̀ wọn, iké àwọn ràkúnmí sì ni wọ́n fi ru àwọn ìpèsè wọn.” (Aísáyà 30:6a) Ó dájú pé ṣe ni wọ́n dìídì wéwèé ìrìn àjò yẹn. Àwọn aṣojú wọ̀nyẹn to àwọn ràkúnmí àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ̀ọ̀wọ́, wọ́n di àwọn ẹrù iyebíye rù wọ́n, wọ́n sì dà wọ́n gba inú aginjù aṣálẹ̀ tí àwọn kìnnìún tí ń kùn hùn-ùn àti ejò olóró pọ̀ sí, lọ sí Íjíbítì. Níkẹyìn, àwọn aṣojú wọ̀nyí dé Íjíbítì níbi tí wọ́n ń lọ, wọ́n sì kó ìṣúra wọn fún àwọn ará ibẹ̀. Lójú tiwọn, ṣe ni wọ́n ti fowó ra ààbò. Ṣùgbọ́n, Jèhófà sọ pé: “Wọn kì yóò já sí àǹfààní kankan fún àwọn ènìyàn náà. Asán gbáà sì ni àwọn ará Íjíbítì, wọn kì yóò sì ṣe ìrànlọ́wọ́ kankan. Nítorí náà, mo ti pe ẹni yìí ní: ‘Ráhábù—wọ́n wà fún jíjókòó jẹ́ẹ́.’” (Aísáyà 30:6b, 7) “Ráhábù,” tí i ṣe “ẹran ńlá abàmì inú òkun,” ló ṣàpẹẹrẹ Íjíbítì. (Aísáyà 51:9, 10) Kò sóhun tí Íjíbítì ò ṣèlérí pé òun máa ṣe, bẹ́ẹ̀ kò ṣe ohunkóhun. Àṣìṣe tó léwu gbáà ni Júdà ṣe tó fi lọ bá a mulẹ̀.
6 Bí Aísáyà ṣe ń ṣàlàyé ìrìn àjò àwọn aṣojú wọ̀nyẹn, ó ṣeé ṣe kí àwọn tó ń gbọ́ ọ rántí irú ìrìn àjò kan náà tó wáyé nígbà ayé Mósè. Inú “aginjù ńlá àti amúnikún-fún-ẹ̀rù” yẹn náà làwọn baba ńlá wọ́n gbà kọjá. (Diutarónómì 8:14-16) Àmọ́, nígbà ayé Mósè, ṣe làwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń jáde lọ kúrò lóko ẹrú ní Íjíbítì. Lọ́tẹ̀ yìí, ṣe làwọn aṣojú wọ̀nyí gbéra lọ sí Íjíbítì, wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ sọ ara wọn dẹni àmúsìn. Wọ́n mà kúkú hùwà òmùgọ̀ o! Ǹjẹ́ kí àwa náà má lọ ṣe irú ìpinnu omùgọ̀ yẹn láé, nípa sísọ ara wa dẹrú dípò wíwà lómìnira nípa tẹ̀mí!—Fi wé Gálátíà 5:1.
-
-
Ẹ Máa Bá A Lọ Láti Fojú Sọ́nà fún JèhófàÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 305]
Nígbà ayé Mósè, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bọ́ lọ́wọ́ Íjíbítì. Nígbà ayé Aísáyà, Júdà tọ Íjíbítì lọ fún ìrànlọ́wọ́
-