ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọba àti Àwọn Ọmọ Aládé Rẹ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • 5-7. Ipa wo ni “àwọn ọmọ aládé” táa sọ tẹ́lẹ̀ ń kó láàárín agbo Ọlọ́run?

      5 Àmọ́ ṣá, níwọ̀n ìgbà tí ayé tó kún fún ìwà ìkórìíra yìí bá ṣì wà, àwọn tó para pọ̀ jẹ́ ogunlọ́gọ̀ yìí ń fẹ́ ààbò. “Àwọn ọmọ aládé” tó ń “ṣàkóso . . . fún ìdájọ́ òdodo” ló sì ń pèsè ààbò yìí ní pàtàkì. Áà, ìṣètò yìí mà ga lọ́lá o! Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà fi àwọn ọ̀rọ̀ tó gbámúṣé ṣàpèjúwe “àwọn ọmọ aládé” wọ̀nyí síwájú sí i pé: “Olúkúlùkù yóò sì wá dà bí ibi ìfarapamọ́sí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀fúùfù àti ibi ìlùmọ́ kúrò lọ́wọ́ ìjì òjò, bí àwọn ìṣàn omi ní ilẹ̀ aláìlómi, bí òjìji àpáta gàǹgà ní ilẹ̀ gbígbẹ táútáú.”—Aísáyà 32:2.

      6 Ní àsìkò yìí gan-an tí ìpọ́njú kárí ayé, a nílò “àwọn ọmọ aládé,” bẹ́ẹ̀ ni o, àní àwọn alàgbà tí yóò “kíyè sí . . . gbogbo agbo,” nípa bíbójútó àwọn àgùntàn Jèhófà, kí wọ́n sì máa ṣe ìdájọ́ òdodo níbàámu pẹ̀lú àwọn ìlànà òdodo Jèhófà. (Ìṣe 20:28) Irú “àwọn ọmọ aládé” bẹ́ẹ̀ ní láti dójú ìlà àwọn ẹ̀rí ìtóótun tó wà nínú Tímótì kìíní, orí kẹta, ẹsẹ kejì sí keje àti Títù orí kìíní, ẹsẹ kẹfà sí ìkẹsàn-án.

      7 Nínú àsọtẹ́lẹ̀ ńlá tí Jésù fi ń ṣàpèjúwe “ìparí ètò àwọn nǹkan” tí yóò kún fún ìpọ́njú, ó sọ pé: “Ẹ rí i pé ẹ kò jáyà.” (Mátíù 24:3-8) Èé ṣe tí ipò inú ayé eléwu òde òní kò fi já àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù láyà? Ìdí kan ni pé, ńṣe ni “àwọn ọmọ aládé,” yálà ẹni àmì òróró tàbí “àgùntàn mìíràn,” ń fi ìdúróṣinṣin dáàbò bo agbo. (Jòhánù 10:16) Láìbẹ̀rù, wọ́n ń bójú tó àwọn arákùnrin àti arábìnrin wọn, kódà lójú ìwà ìkà bí ogun láàárín ẹ̀yà kan àti òmíràn, àti ìpẹ̀yàrun. Nínú ayé tí ohun tẹ̀mí ti ṣọ̀wọ́n yìí, wọ́n ń rí i dájú pé àwọn tó ní ìdààmú ọkàn ń rí òtítọ́ tó ń gbéni ró gbà látinú Bíbélì, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, èyí sì ń tù wọ́n lára.

      8. Báwo ni Jèhófà ṣe ń dá “àwọn ọmọ aládé” tó jẹ́ ara àwọn àgùntàn mìíràn lẹ́kọ̀ọ́?

      8 Láti àádọ́ta ọdún síhìn-ín ni “àwọn ọmọ aládé” ti túbọ̀ hàn kedere sójú táyé. “Àwọn ọmọ aládé” tó jẹ́ ara àwọn àgùntàn mìíràn sì ń gba ìdánilẹ́kọ̀ọ́ gẹ́gẹ́ bí ara ẹgbẹ́ “ìjòyè” tó ń yọjú bọ̀, kí ó lè jẹ́ pé, lẹ́yìn ìpọ́njú ńlá, àwọn tó tóótun lára wọn yóò wà ní sẹpẹ́ láti gba ẹrù iṣẹ́ àbójútó nínú “ayé tuntun.” (Ìsíkíẹ́lì 44:2, 3; 2 Pétérù 3:13) Wọ́n ń fi hàn pé àwọn dà “bí òjìji àpáta gàǹgà” nípa pípèsè tí wọ́n ń pèsè ìtọ́sọ́nà àti ìtura bí wọ́n ṣe ń mú ipò iwájú nínú iṣẹ́ ìsìn Ìjọba Ọlọ́run, wọ́n sì ń tipa báyìí mú ìtura bá agbo nínú gbogbo ohun tó jẹ mọ́ ìjọsìn wọn.b

      9. Àwọn ipò wo ló fi hàn pé a nílò “àwọn ọmọ aládé” lóde òní?

      9 Nínú àwọn ọjọ́ ìkẹyìn eléwu ti ayé búburú, ayé Sátánì yìí, àwọn Kristẹni tó ṣe ìyàsímímọ́ ń fẹ́ ààbò yìí gidigidi. (2 Tímótì 3:1-5, 13) Ẹ̀fúùfù líle ti ẹ̀kọ́ èké àti ìgbékèéyíde ń fẹ́. Ìjì ogun ń jà lọ ràì, àní ogun láàárín orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè àti ogun abẹ́lé, ìyẹn nìkan kọ́ o, àwọn èèyàn tún ń dojú ìjà kọ àwọn olóòótọ́ olùjọsìn Jèhófà Ọlọ́run. Inú ayé tó gbẹ táútáú nítorí ọ̀dá ohun tẹ̀mí yìí sì làwọn Kristẹni wà, nítorí náà, wọ́n nílò ìṣàn omi òtítọ́ gan-an ni, omi tó mọ́ tónítóní, tí kò lábùlà, láti lè fi pòùngbẹ wọn nípa tẹ̀mí. Ó sì dùn mọ́ni pé Jèhófà ṣèlérí pé Ọba tóun fi jẹ yìí yóò lo àwọn arákùnrin rẹ̀ ẹni àmì òróró, àti “àwọn ọmọ aládé” látinú àwọn àgùntàn mìíràn tó ń tì wọ́n lẹ́yìn, láti fi pèsè ìṣírí àti ìtọ́sọ́nà fún àwọn tí ìdààmú ọkàn àti ìrẹ̀wẹ̀sì bá lákòókò ìnira yìí. Nípa bẹ́ẹ̀, Jèhófà yóò rí sí i pé ohun tó tọ́, tó sì bá ìdájọ́ òdodo mu ni yóò gbilẹ̀.

  • Ọba àti Àwọn Ọmọ Aládé Rẹ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • [Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 333]

      Olúkúlùkù “ọmọ aládé” dà bí ibi ìfarapamọ́sí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀fúùfù àti ibi ìlùmọ́ kúrò lọ́wọ́ òjò, bí omi ní ilẹ̀ aláìlómi, àti bí òjìji kúrò lọ́wọ́ oòrùn

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́