-
Ìdájọ́ Jehofa Lòdìsí Àwọn Olùkọ́ni ÈkéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | March 1
-
-
17. (a) Gẹ́gẹ́ bí Jeremiah ti sọ, irú ìdájọ́ wo ni yóò wá sórí Jerusalemu búburú? (b) Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí Kristẹndọm láìpẹ́?
17 Irú ìdájọ́ wo ni àwọn olùkọ́ni èké Kristẹndọm yóò rí gbà lọ́dọ̀ Jehofa, Onídàájọ́ ńlá náà? Ẹsẹ 19, 20, 39, àti 40 dáhùn pé: “Sá wò ó, afẹ́fẹ́-ìjì Oluwa! ìbínú ti jáde! àfẹ́yíká ìjì yóò ṣubú ní ìkanra sí orí àwọn olùṣe búburú: Ìbínú Oluwa kì yóò padà, títí yóò fi ṣe é, títí yóò sì fi mú ìrò inú rẹ̀ ṣẹ. . . . Èmi ó gbàgbé yín pátápátá, èmi ó sì kọ̀ yín sílẹ̀, èmi ó sì tì yín jáde, àti ìlú tí mo fi fún yín àti fún àwọn baba yín, kúrò níwájú mi. Èmi ó sì mú ẹ̀gàn àìnípẹ̀kun wá sórí yín, àti ìtìjú láéláé, tí a kì yóò gbàgbé.” Gbogbo ìyẹn ṣẹlẹ̀ sí Jerusalemu oníwà burúkú àti tẹ́ḿpìlì rẹ̀, irú àjálù kan náà kò ní pẹ́ jálu Kristẹndọm oníwà burúkú nísinsìnyí!
-
-
Ìdájọ́ Jehofa Lòdìsí Àwọn Olùkọ́ni ÈkéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | March 1
-
-
21. (a) Èéṣe tí a fi pa Jerusalemu run ní 607 B.C.E.? (b) Lẹ́yìn ìparun Jerusalemu, kí ni o ṣẹlẹ̀ sí àwọn wòlíì èké àti àwọn wòlíì tòótọ́ ti Jehofa, ní fífún wa ni ìdánilójú wo lónìí?
21 A mú ìdájọ́ Jehofa ṣẹ ní ọjọ́ Jeremiah nígbà tí awọn ará Babiloni pa Jerusalemu run ní 607 B.C.E. Gẹ́gẹ́ bí a ti sọtẹ́lẹ̀, ìyẹn jẹ́ ‘ẹ̀gàn àti ìtìjú’ fún àwọn ọmọ Israeli alágídí, aláìgbàgbọ́ wọnnì. (Jeremiah 23:39, 40) Ó fihàn wọ́n pé Jehofa, tí wọ́n ti kẹ́gàn bá léraléra, ti kọ̀ wọ́n tì fún àwọn àbájáde ìwà ibi wọn nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín. Àwọn ọ̀yájú wòlíì èké wọn ni a palẹ́numọ́ nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín. Síbẹ̀, ẹnu Jeremiah ń sọtẹ́lẹ̀ nìṣó. Jehofa kò kọ̀ ọ́ tì. Ní títẹ̀lé àwòkọ́ṣe yìí, Jehofa kì yóò pa ẹgbẹ́ Jeremiah tì nígbà tí ìpinnu wíwúwo rẹ̀ bá yọrísí gbígbẹ̀mí àwọn àlùfáà Kristẹndọm àti àwọn wọnnì tí wọ́n gba èké wọn gbọ́.
-