-
You Can Benefit From the New CovenantỌ̀rọ̀ Tí Ọlọ́run Bá Wa Sọ Nípasẹ̀ Jeremáyà
-
-
5. Kí nìdí tí Jèhófà fi sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa májẹ̀mú tuntun kan?
5 A lè wá rídìí tó fi jẹ́ pé nígbà tí wọ́n ṣì wà lábẹ́ májẹ̀mú Òfin, Ọlọ́run mí sí Jeremáyà láti sọ tẹ́lẹ̀ nípa májẹ̀mú míì, ìyẹn májẹ̀mú tuntun. Nítorí inú rere àti ìfẹ́ tí Jèhófà ní, ó fẹ́ ṣe ìrànlọ́wọ́ kan tó máa wà títí gbére tí àǹfààní rẹ̀ ò sì ní mọ sí orílẹ̀-èdè kan ṣoṣo. Ọlọ́run gbẹnu Jeremáyà sọ̀rọ̀ nípa àwọn tó máa wà nínú májẹ̀mú tuntun ọjọ́ iwájú yìí pé: “Èmi yóò dárí ìṣìnà wọn jì, ẹ̀ṣẹ̀ wọn ni èmi kì yóò sì rántí mọ́.” (Jer. 31:34) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ìgbà ayé Jeremáyà ni Ọlọ́run ṣe ìlérí yìí, gbogbo aráyé ló máa ṣe láǹfààní ńláǹlà lọ́jọ́ ọ̀la. Lọ́nà wo?
6, 7. (a) Báwo ló ṣe máa ń rí lára àwọn kan pé wọ́n jẹ́ni tó ń dẹ́ṣẹ̀? (b) Kí nìdí tí ṣíṣàyẹ̀wò májẹ̀mú tuntun fi lè múnú rẹ dùn?
6 Aláìpé ṣì ni wá, àìpé yìí sì máa ń jẹ yọ lára wa lọ́pọ̀ ìgbà. A rí àpẹẹrẹ èyí lára arákùnrin kan tó ń sa gbogbo ipá rẹ̀ láti borí ìṣòro kan tí kò lọ bọ̀rọ̀. Ó ní: “Ìbànújẹ́ máa ń bá mi nígbà tí mo bá tún jìn sọ́fìn ìwà tí mò ń sapá láti borí. Mo máa ń rò pé kò sí ohun tí mo lè ṣe tí Ọlọ́run á fi dárí jì mí. Àtigbàdúrà gan-an máa ń dogun fún mi. Tí mo bá jàjà fẹ́ gbàdúrà mo máa ń bẹ̀rẹ̀ báyìí pé, ‘Jèhófà, mi ò mọ̀ bóyá wàá gbọ́ àdúrà mi yìí, àmọ́ . . . ’” Bákan náà, ó máa ń ṣe àwọn míì tó tún pa dà jìn sọ́fìn ìwà àìtọ́, tàbí àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ kan, bí ẹni pé “ìwọ́jọpọ̀ àwọsánmà” dínà mọ́ àdúrà wọn kó má lè dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run. (Ìdárò 3:44) Ìdààmú ṣì máa ń bá àwọn míì lórí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ̀ sẹ́yìn, àní lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún tí wọ́n ti dá ẹ̀ṣẹ̀ náà. Kódà, Kristẹni kan tó jẹ́ àpẹẹrẹ rere pàápàá lè sọ ohun kan táá tún wá kábàámọ̀ rẹ̀ pé òun ì bá má ti sọ ọ́.—Ják. 3:5-10.
7 Kí ẹnikẹ́ni nínú wa má rò pé òun ò lè ṣe ohun tó kù díẹ̀ káàtó láéláé, torí a kì í rìn kí orí má mì. (1 Kọ́r. 10:12) Kódà àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù alára rí i pé òun pàápàá ò bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀. (Ka Róòmù 7:21-25.) Ibi tí ọ̀rọ̀ ti kan májẹ̀mú tuntun gan-an nìyí. Ọlọ́run ṣèlérí pé ohun pàtàkì kan tó máa wáyé nínú májẹ̀mú tuntun yìí ni pé òun ò ní máa rántí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn èèyàn mọ́. Àǹfààní tí kò láfiwé gbáà lèyí máa ṣe fún wa! Yóò dùn mọ́ Jeremáyà nínú gan-an bó ṣe ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, àní bó ṣe máa dùn mọ́ àwa náà bá a ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀ tá a sì ń rí ọ̀nà tó lè gbà ṣe wá láǹfààní.
-
-
You Can Benefit From the New CovenantỌ̀rọ̀ Tí Ọlọ́run Bá Wa Sọ Nípasẹ̀ Jeremáyà
-
-
8, 9. Kí ló ná Jèhófà kí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ tó lè ṣeé ṣe?
8 Bó o ṣe ń mọ Jèhófà sí i ni wàá túbọ̀ máa rí bó ṣe jẹ́ onínúure àti aláàánú tó sí ẹ̀dá èèyàn aláìpé. (Sm. 103:13, 14) Nígbà tí Jeremáyà ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa májẹ̀mú tuntun, ó sọ ọ́ kedere pé Jèhófà máa “dárí ìṣìnà wọn jì” kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́. (Jer. 31:34) Àmọ́ Jeremáyà tiẹ̀ lè máa rò ó pé ọ̀nà wo ni Ọlọ́run máa gbé ọ̀rọ̀ ìdáríjì yìí gbà ná? Yóò ṣáà mọ̀ pé bí Ọlọ́run ṣe sọ̀rọ̀ nípa májẹ̀mú tuntun yìí, ṣe ló máa bá aráyé wọ àdéhùn kan. Àti pé, lọ́nà kan ṣáá, Jèhófà máa tipa májẹ̀mú yẹn mú ohun tó mí sí òun láti kọ sílẹ̀ ṣẹ, títí kan ọ̀rọ̀ ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀. Tó bá sì wá tásìkò lójú Ọlọ́run yóò máa ṣí àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ tó kù nínú ète rẹ̀ payá, títí kan ohun tí Mèsáyà máa ṣe.
9 Ó ṣeé ṣe kó o ti máa rí àwọn òbí tó kẹ́ ọmọ wọn lákẹ̀ẹ́bàjẹ́, tí wọn kì í bá a wí. Ǹjẹ́ o rò pé Jèhófà máa ṣerú nǹkan bẹ́ẹ̀? Ó tì o! A rí èyí kedere nínú ọ̀nà tí májẹ̀mú tuntun yẹn gbà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́. Ọlọ́run ò kàn dédé wọ́gi lé ẹ̀ṣẹ̀ aráyé. Kàkà bẹ́ẹ̀ ṣe ló fẹ̀sọ̀ tẹ̀ lé gbogbo ìlànà ìdájọ́ òdodo rẹ̀, tó ṣètò ọ̀nà tó bófin mu tá a ó fi lè máa rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà, bó tiẹ̀ jẹ́ pé nǹkan ńláǹlà ló ná an. O lè túbọ̀ lóye èyí tó o bá kíyè sí ohun tí Pọ́ọ̀lù sọ nígbà tó ń ṣàlàyé májẹ̀mú tuntun. (Ka Hébérù 9:15, 22, 28.) Pọ́ọ̀lù mẹ́nu kan ‘ìtúsílẹ̀ nípasẹ̀ ìràpadà,’ ó wá sọ pé “bí kò sì ṣe pé a tú ẹ̀jẹ̀ jáde, ìdáríjì kankan kì í wáyé.” Ẹ̀jẹ̀ inú májẹ̀mú tuntun tíbí yìí ń sọ kì í ṣe ẹ̀jẹ̀ màlúù tàbí ti ewúrẹ́ tí wọ́n sábà máa fi ń rúbọ lábẹ́ májẹ̀mú Òfin o. Ẹ̀jẹ̀ Jésù ló mú kí májẹ̀mú tuntun yìí ṣeé ṣe. Lọ́lá ẹbọ Jésù yìí, tó jẹ́ ẹbọ pípé, Jèhófà lè máa ‘dárí ìṣìnà àti ẹ̀ṣẹ̀ jì’ títí láé. (Ìṣe 2:38; 3:19) Àmọ́ àwọn wo ló máa kópa nínú májẹ̀mú tuntun yẹn tí wọ́n á sì rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yìí gbà? Orílẹ̀-èdè àwọn Júù kọ́ o. Torí Jésù sọ pé Ọlọ́run yóò kọ àwọn Júù, tó jẹ́ pé wọ́n ń fi ẹran rúbọ lábẹ́ májẹ̀mú Òfin, yóò sì yíjú sí orílẹ̀-èdè mìíràn. (Mát. 21:43; Ìṣe 3:13-15) “Ísírẹ́lì Ọlọ́run,” ìyẹn àwọn Kristẹni tí Ọlọ́run fi ẹ̀mí mímọ́ yàn, ló para pọ̀ jẹ́ orílẹ̀-èdè yìí. Ní kúkúrú, májẹ̀mú Òfin ló wà láàárín Ọlọ́run àti orílẹ̀-èdè àwọn Júù, tí májẹ̀mú tuntun sì wà láàárín Jèhófà Ọlọ́run àti Ísírẹ́lì tẹ̀mí, Jésù sì ni Alárinà rẹ̀.—Gál. 6:16; Róòmù 9:6.
10. (a) Ta ni “èéhù” Dáfídì? (b) Báwo ni aráyé ṣe lè jàǹfààní lára “èéhù” yìí?
10 Jeremáyà sọ pé Ẹni tó ń bọ̀, ìyẹn Mèsáyà, jẹ́ “èéhù” Dáfídì. Ó sì bá a mu bẹ́ẹ̀. Nítorí pé Jeremáyà ò tiẹ̀ tíì kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wòlíì nígbà tí wọ́n ti yẹ àga mọ́ àwọn ọba tó ń jẹ láti ìlà ìdílé Dáfídì nídìí, tí wọ́n gé ìlà àwọn ọba náà lulẹ̀ bí ẹni gé igi. Àmọ́ kùkùté rẹ̀ kò kú. Nígbà tó yá, wọ́n bí Jésù ní ìlà ìdílé Dáfídì Ọba. Òun lẹni tá a lè pè ní “Jèhófà Ni Òdodo Wa,” èyí tó fi hàn pé Ọlọ́run fẹ́ràn òdodo gan-an ni. (Ka Jeremáyà 23:5, 6.) Jèhófà gbà kí Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo yìí jìyà lórí ilẹ̀ ayé kó sì kú. Ó wá ṣeé ṣe fún Jèhófà láti ṣe ohun tó bá ìdájọ́ òdodo mu, kó lo ìtóye ẹbọ ìràpadà tí Ọmọ rẹ̀ tó jẹ́ “èéhù” Dáfídì yìí fara rẹ̀ rú, láti fi ṣe ìpìlẹ̀ fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀. (Jer. 33:15) Èyí jẹ́ kí àwọn èèyàn kan dẹni tí Ọlọ́run lè polongo ní “olódodo fún ìyè,” kó fẹ̀mí mímọ́ yàn wọ́n, kí wọ́n sì kópa nínú májẹ̀mú tuntun náà. Ẹ̀rí pé Ọlọ́run fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo sì tún hàn síwájú sí i ní ti pé àwọn míì tí kò kópa ní tààràtà nínú májẹ̀mú yẹn náà lè jàǹfààní nínú rẹ̀, wọ́n sì ti ń jàǹfààní rẹ̀ báyìí, gẹ́gẹ́ bá a ṣe máa rí i níwájú.—Róòmù 5:18.
-