-
“Èmi Yóò Yan Olùṣọ́ Àgùntàn Kan”Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
5. Àlọ́ wo ni Jèhófà ní kí Ìsíkíẹ́lì pa?
5 Ka Ìsíkíẹ́lì 17:3-10. Bí àlọ́ náà ṣe lọ nìyí: “Ẹyẹ idì ńlá” kan já ọ̀mùnú tó wà lókè pátápátá lórí igi kédárì kan, ó lọ gbìn ín “sí ìlú àwọn oníṣòwò.” Ẹyẹ idì náà wá mú “lára irúgbìn ilẹ̀ náà” ó sì gbìn ín sórí ilẹ̀ tó lọ́ràá “lẹ́gbẹ̀ẹ́ alagbalúgbú omi.” Irúgbìn náà rú jáde, ó dàgbà, ó sì di ‘àjàrà tó bolẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, “ẹyẹ idì ńlá” míì fò wá. Gbòǹgbò àjàrà náà wá ‘yára lọ’ sọ́dọ̀ ẹyẹ idì kejì yìí, ó fẹ́ kí ẹyẹ idì náà lọ gbin òun síbòmíì tó lómi dáadáa. Inú Jèhófà ò dùn rárá sí ohun tí àjàrà yìí ṣe, ó sì sọ pé wọ́n máa fa gbòǹgbò rẹ̀ tu àti pé ṣe ló máa “gbẹ dà nù.”
Ẹyẹ idì ńlá àkọ́kọ́ ṣàpẹẹrẹ Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (Wo ìpínrọ̀ 6)
6. Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà?
6 Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà? (Ka Ìsíkíẹ́lì 17:11-15.) Lọ́dún 617 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” àkọ́kọ́) gbógun wá sí Jerúsálẹ́mù. Ó mú Jèhóákínì Ọba Júdà (ìyẹn ‘ọ̀mùnú tó wà lókè pátápátá’) kúrò lórí ìtẹ́, ó sì mú un wá sí Bábílónì (ìyẹn “ìlú àwọn oníṣòwò”). Nebukadinésárì fi Sedekáyà (tó jẹ́ ọ̀kan lára “irúgbìn ilẹ̀ náà” tó ń jọba) sórí ìtẹ́ ní Jerúsálẹ́mù. Wọ́n ní kí ọba tuntun tó jẹ ní Júdà yìí fi orúkọ Ọlọ́run búra pé òun á máa fi ara òun sábẹ́ ọba Bábílónì nígbà gbogbo, òun á sì jẹ́ olóòótọ́ sí i. (2 Kíró. 36:13) Àmọ́ Sedekáyà ò ka ìbúra yẹn sí; ó ṣọ̀tẹ̀ sí Bábílónì nígbà tó fẹ́ jagun, ó wá ìrànlọ́wọ́ lọ sọ́dọ̀ Fáráò ní Íjíbítì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” kejì), àmọ́ pàbó ni ìsapá rẹ̀ já sí. Inú Jèhófà ò dùn rárá sí ìwà àìṣòótọ́ àti ìwà ọ̀dàlẹ̀ tí Sedekáyà hù yìí. (Ìsík. 17:16-21) Nígbà tó yá, wọ́n gbàjọba lọ́wọ́ rẹ̀, inú ẹ̀wọ̀n ló sì kú sí ní Bábílónì.—Jer. 52:6-11.
-
-
Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Mèsáyà—Igi Kédárì ŃláÌjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
3. Sedekáyà ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà, ó wá ìrànlọ́wọ́ lọ sí Íjíbítì nígbà tó fẹ́ jagun
-