ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Èmi Yóò Yan Olùṣọ́ Àgùntàn Kan”
    Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
    • Ẹyẹ idì kan já ọ̀mùnú igi kédárì.

      Ẹyẹ idì ńlá àkọ́kọ́ ṣàpẹẹrẹ Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (Wo ìpínrọ̀ 6)

      6. Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà?

      6 Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà? (Ka Ìsíkíẹ́lì 17:11-15.) Lọ́dún 617 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” àkọ́kọ́) gbógun wá sí Jerúsálẹ́mù. Ó mú Jèhóákínì Ọba Júdà (ìyẹn ‘ọ̀mùnú tó wà lókè pátápátá’) kúrò lórí ìtẹ́, ó sì mú un wá sí Bábílónì (ìyẹn “ìlú àwọn oníṣòwò”). Nebukadinésárì fi Sedekáyà (tó jẹ́ ọ̀kan lára “irúgbìn ilẹ̀ náà” tó ń jọba) sórí ìtẹ́ ní Jerúsálẹ́mù. Wọ́n ní kí ọba tuntun tó jẹ ní Júdà yìí fi orúkọ Ọlọ́run búra pé òun á máa fi ara òun sábẹ́ ọba Bábílónì nígbà gbogbo, òun á sì jẹ́ olóòótọ́ sí i. (2 Kíró. 36:13) Àmọ́ Sedekáyà ò ka ìbúra yẹn sí; ó ṣọ̀tẹ̀ sí Bábílónì nígbà tó fẹ́ jagun, ó wá ìrànlọ́wọ́ lọ sọ́dọ̀ Fáráò ní Íjíbítì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” kejì), àmọ́ pàbó ni ìsapá rẹ̀ já sí. Inú Jèhófà ò dùn rárá sí ìwà àìṣòótọ́ àti ìwà ọ̀dàlẹ̀ tí Sedekáyà hù yìí. (Ìsík. 17:​16-21) Nígbà tó yá, wọ́n gbàjọba lọ́wọ́ rẹ̀, inú ẹ̀wọ̀n ló sì kú sí ní Bábílónì.​—Jer. 52:6-11.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Mèsáyà​—Igi Kédárì Ńlá
    Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
      • Ẹyẹ idì kan ń fi èékánná rẹ̀ gbé ọ̀mùnú igi kédárì lọ sí Bábílónì.

        1. Nebukadinésárì mú Jèhóákínì lọ sí Bábílónì

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́