-
“Èmi Yóò Yan Olùṣọ́ Àgùntàn Kan”Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
Ẹyẹ idì ńlá àkọ́kọ́ ṣàpẹẹrẹ Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (Wo ìpínrọ̀ 6)
6. Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà?
6 Kí ni ìtúmọ̀ àlọ́ náà? (Ka Ìsíkíẹ́lì 17:11-15.) Lọ́dún 617 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, Nebukadinésárì Ọba Bábílónì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” àkọ́kọ́) gbógun wá sí Jerúsálẹ́mù. Ó mú Jèhóákínì Ọba Júdà (ìyẹn ‘ọ̀mùnú tó wà lókè pátápátá’) kúrò lórí ìtẹ́, ó sì mú un wá sí Bábílónì (ìyẹn “ìlú àwọn oníṣòwò”). Nebukadinésárì fi Sedekáyà (tó jẹ́ ọ̀kan lára “irúgbìn ilẹ̀ náà” tó ń jọba) sórí ìtẹ́ ní Jerúsálẹ́mù. Wọ́n ní kí ọba tuntun tó jẹ ní Júdà yìí fi orúkọ Ọlọ́run búra pé òun á máa fi ara òun sábẹ́ ọba Bábílónì nígbà gbogbo, òun á sì jẹ́ olóòótọ́ sí i. (2 Kíró. 36:13) Àmọ́ Sedekáyà ò ka ìbúra yẹn sí; ó ṣọ̀tẹ̀ sí Bábílónì nígbà tó fẹ́ jagun, ó wá ìrànlọ́wọ́ lọ sọ́dọ̀ Fáráò ní Íjíbítì (ìyẹn “ẹyẹ idì ńlá” kejì), àmọ́ pàbó ni ìsapá rẹ̀ já sí. Inú Jèhófà ò dùn rárá sí ìwà àìṣòótọ́ àti ìwà ọ̀dàlẹ̀ tí Sedekáyà hù yìí. (Ìsík. 17:16-21) Nígbà tó yá, wọ́n gbàjọba lọ́wọ́ rẹ̀, inú ẹ̀wọ̀n ló sì kú sí ní Bábílónì.—Jer. 52:6-11.
-
-
Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Mèsáyà—Igi Kédárì ŃláÌjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
1. Nebukadinésárì mú Jèhóákínì lọ sí Bábílónì
-