-
‘Gbogbo Ohun Tó Wà Níbi tí Omi Náà Ṣàn Dé Yóò Máa Wà Láàyè’Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
1, 2. Bí Ìsíkíẹ́lì 47:1-12 ṣe sọ, kí ni Ìsíkíẹ́lì rí, ẹ̀kọ́ wo ló sì kọ? (Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ orí yìí.)
ÌSÍKÍẸ́LÌ tún rí ohun àrà míì nínú ìran tẹ́ńpìlì náà: Ó rí omi tó ń ṣàn jáde látinú ibi mímọ́! Ẹ fojú inú wo bí Ìsíkíẹ́lì ṣe ń tọpasẹ̀ omi tó mọ́ lóló náà lọ kó lè mọ ibi tó ti ń ṣàn wá. (Ka Ìsíkíẹ́lì 47:1-12.) Omi náà rọra ń sun látẹnu ọ̀nà tẹ́ńpìlì; ó sì ṣàn jáde gba inú àgbàlá tẹ́ńpìlì tó wà nítòsí ẹnubodè ìlà oòrùn. Áńgẹ́lì tó ń fi ìran han Ìsíkíẹ́lì mú un jáde kúrò nínú tẹ́ńpìlì, ó sì ń wọn ìrìn wọn àti jíjìn omi náà bí wọ́n ṣe ń lọ. Áńgẹ́lì náà ń sọ fún Ìsíkíẹ́lì léraléra pé kó gba inú omi náà kọjá, wòlíì náà sì ń rí i pé ṣe lomi náà ń yára kún sí i bí wọ́n ṣe ń lọ, kò pẹ́ tómi yìí fi di alagbalúgbú tí kò ṣeé fi ẹsẹ̀ là kọjá, àfi kéèyàn lúwẹ̀ẹ́!
-
-
‘Gbogbo Ohun Tó Wà Níbi tí Omi Náà Ṣàn Dé Yóò Máa Wà Láàyè’Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
4. (a) Àwọn ìbùkún wo ni àwọn Júù á máa retí látọ̀dọ̀ Jèhófà bí wọ́n ṣe gbọ́ nípa odò tí Ìsíkíẹ́lì rí nínú ìran? (b) Báwo ni bí Bíbélì ṣe ń lo “odò” àti “omi” ṣe fi dá wa lójú pé Jèhófà máa bù kún àwọn èèyàn rẹ̀? (Wo àpótí náà, “Àwọn Odò Ìbùkún Látọ̀dọ̀ Jèhófà.”)
4 Odò ìbùkún. Nínú Bíbélì, wọ́n sábà máa ń fi odò àti omi ṣàpèjúwe bí ìbùkún Jèhófà tó ń fúnni ní ìyè ṣe ń ṣàn. Irú odò yìí ni Ìsíkíẹ́lì rí tó ń ṣàn jáde látinú tẹ́ńpìlì, torí náà, ìran yìí á ti mú kí àwọn èèyàn Ọlọ́run máa retí pé ìbùkún Jèhófà tó ń fúnni ní ìyè máa ṣàn dé ọ̀dọ̀ wọn tí wọn ò bá yéé ṣe ìjọsìn mímọ́. Àwọn ìbùkún wo nìyẹn? Wọ́n á tún máa gba ìtọ́ni tẹ̀mí látọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà. Bí wọ́n sì ṣe ń rúbọ ní tẹ́ńpìlì, á tún dá wọn lójú pé ètùtù yẹn máa ṣiṣẹ́ fún ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn. (Ìsík. 44:15, 23; 45:17) Torí náà, wọ́n á tún wà ní mímọ́ lẹ́ẹ̀kan sí i, bíi pé wọ́n fi omi tó mọ́ lóló tó ń tú jáde látinú tẹ́ńpìlì wẹ̀.
-