-
“Pín Ilẹ̀ Náà Bí Ogún”Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
‘Mo Pín Ilẹ̀ Yìí fún Yín Láti Jẹ́ Ogún Yín’
5, 6. (a) Nínú ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí, ilẹ̀ wo ni wọ́n máa pín? (Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ orí yìí.) (b) Kí lohun tí ìran nípa pínpín ilẹ̀ náà wà fún?
5 Ka Ìsíkíẹ́lì 47:14. Jèhófà mú kí Ìsíkíẹ́lì rí ilẹ̀ kan nínú ìran, ìyẹn ilẹ̀ tó máa tó dà bí “ọgbà Édẹ́nì.” (Ìsík. 36:35) Jèhófà wá sọ pé: “Ilẹ̀ tí ẹ máa yàn bí ogún fún ẹ̀yà Ísírẹ́lì méjìlá (12) nìyí.” (Ìsík. 47:13) “Ilẹ̀” tí wọ́n máa pín ni ilẹ̀ Ísírẹ́lì tó ti pa dà bọ̀ sípò, èyí tí àwọn tó wà nígbèkùn máa pa dà sí. Lẹ́yìn náà, Jèhófà sọ kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa ààlà tó wà ní eteetí ilẹ̀ náà, bó ṣe wà nínú Ìsíkíẹ́lì 47:15-21.
6 Kí lohun tí ìran nípa pínpín ilẹ̀ yìí wà fún? Ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn ibi tí ààlà ilẹ̀ náà dé mú kó dá Ìsíkíẹ́lì àtàwọn tí wọ́n jọ wà nígbèkùn lójú pé ilẹ̀ wọn tí wọ́n fẹ́ràn máa pa dà sí bó ṣe wà tẹ́lẹ̀. Fojú inú wo bí ìdánilójú tí Jèhófà fún àwọn tó wà nígbèkùn ṣe máa rí lára wọn, ó dájú pé inú wọn máa dùn sí kúlẹ̀kúlẹ̀ àlàyé tí Jèhófà ṣe lọ́nà tó ṣe kedere! Ṣé àwọn èèyàn Ọlọ́run nígbà àtijọ́ gba ilẹ̀ tí wọ́n pín fún wọn pé kí wọ́n jogún lóòótọ́? Bẹ́ẹ̀ ni o, wọ́n gbà á.
7. (a) Àwọn nǹkan wo ló bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹlẹ̀ lọ́dún 537 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, kí nìyẹn sì rán wa létí? (b) Ìbéèrè wo la máa kọ́kọ́ dáhùn?
7 Lọ́dún 537 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni, ìyẹn ọdún mẹ́rìndínlọ́gọ́ta (56) lẹ́yìn tí Ìsíkíẹ́lì rí ìran, ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tó wà nígbèkùn bẹ̀rẹ̀ sí í pa dà sí ilẹ̀ Ísírẹ́lì, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Àwọn ohun mánigbàgbé tó ṣẹlẹ̀ lọ́pọ̀ ọdún sẹ́yìn yẹn rán wa létí pé irú ohun kan náà ti ń ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn èèyàn Ọlọ́run lóde òní. Lọ́nà kan, àwọn náà gba ilẹ̀ tí wọ́n pín fún wọn. Báwo ló ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀? Jèhófà jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ilẹ̀ tẹ̀mí kan, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Torí náà, Ilẹ̀ Ìlérí ayé àtijọ́ tó pa dà bọ̀ sípò kọ́ wa ní ọ̀pọ̀ nǹkan nípa bí ilẹ̀ tẹ̀mí àwọn èèyàn Ọlọ́run òde òní ṣe máa pa dà bọ̀ sípò. Àmọ́ ká tó gbé àwọn ẹ̀kọ́ náà yẹ̀ wò, ẹ jẹ́ ká kọ́kọ́ dáhùn ìbéèré yìí, “Kí nìdí tá a fi gbà pé ilẹ̀ tẹ̀mí kan wà lóde òní lóòótọ́?”
8. (a) Orílẹ̀-èdè wo ni Jèhófà fi rọ́pò orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì tara? (b) Kí ni ilẹ̀ tẹ̀mí tàbí párádísè tẹ̀mí túmọ̀ sí? (d) Ìgbà wo ló wáyé, àwọn wo ló sì ń gbé lórí ilẹ̀ náà?
8 Nínú ìran tí Ìsíkíẹ́lì kọ́kọ́ rí, Jèhófà jẹ́ kó rí i pé àwọn àsọtẹ́lẹ̀ nípa bí Ísírẹ́lì ṣe máa pa dà bọ̀ sípò máa ṣẹ lọ́nà tó gbòòrò lẹ́yìn tí “Dáfídì ìránṣẹ́” rẹ̀, ìyẹn Jésù Kristi, bá bẹ̀rẹ̀ sí í jọba. (Ìsík. 37:24) Ọdún 1914 Sànmánì Kristẹni ni èyí ṣẹlẹ̀. Tipẹ́tipẹ́ ṣáájú ìgbà yẹn ni Ọlọ́run ti fi orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì nípa tẹ̀mí, ìyẹn àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró, rọ́pò orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì nípa tara tí wọ́n jẹ́ èèyàn Ọlọ́run. (Ka Mátíù 21:43; 1 Pétérù 2:9.) Àmọ́, kì í ṣe orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì nípa tẹ̀mí nìkan ni Jèhófà fi rọ́pò orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì nípa tara, ó tún fi ilẹ̀ tẹ̀mí tàbí párádísè tẹ̀mí rọ́pò ilẹ̀ Ísírẹ́lì àtijọ́. (Àìsá. 66:8) Bá a ṣe rí i ní Orí 17 ìwé yìí, ilẹ̀ tẹ̀mí yẹn ni àyíká tẹ̀mí tó ní ààbò tàbí ibi tá a ti ń gbájú mọ́ àwọn nǹkan tẹ̀mí, níbi tí àwọn àṣẹ́kù ẹni àmì òróró ti ń sin Jèhófà látọdún 1919. (Wo àpótí 9B, “Ohun Tó Ṣẹlẹ̀ Lọ́dún 1919”) Bọ́jọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, àwọn tó nírètí láti gbé láyé, ìyẹn àwọn “àgùntàn mìíràn,” bẹ̀rẹ̀ sí í gbé orí ilẹ̀ tẹ̀mí yìí. (Jòh. 10:16) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé párádísè tẹ̀mí ń tura sí i, ó sì ń gbèrú, ó di ẹ̀yìn Amágẹ́dọ́nì ká tó gbádùn ìbùkún ibẹ̀ dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
-
-
“Pín Ilẹ̀ Náà Bí Ogún”Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
13 Àkọ́kọ́, ilẹ̀ náà. Ọlọ́run sọ fún Mósè pé kí ilẹ̀ tó máa pín fún àwọn ẹ̀yà tó tóbi pọ̀ ju èyí tó máa pín fún àwọn ẹ̀yà tí kò tóbi. (Nọ́ń. 26:52-54) Àmọ́, nínú ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí, Jèhófà ní kí wọ́n pín ilẹ̀ fún gbogbo ẹ̀yà, kí “ìpín kálukú . . . sì dọ́gba [“kálukú bí arákùnrin rẹ̀,” àlàyé ìsàlẹ̀].” (Ìsík. 47:14) Torí náà, nínú gbogbo ẹ̀yà méjìlá (12) tí wọ́n pín ogún fún, kò sí ẹni tí ogún tiẹ̀ kéré sí tẹni kejì, ọgbọọgba ni, láti ààlà tó wà ní àríwá títí dé ààlà tó wà ní gúúsù. Gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì pátá, láìka ẹ̀yà tí wọ́n ti wá sí, gbogbo wọn ló jọ máa nípìn-ín nínú ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ oúnjẹ tó ń jáde láti Ilẹ̀ Ìlérí tó jẹ́ ilẹ̀ tó lómi dáadáa.
-