-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
9, 10. (a) Ibo ni Dáníẹ́lì wà nígbà tí ó rí ìran kan? (b) Ṣàpèjúwe ohun tí Dáníẹ́lì rí lójú ìran náà.
9 A kò já Dáníẹ́lì kulẹ̀. Ó ń bá a lọ láti sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn náà fún wa pé: “Ó ṣẹlẹ̀ pé èmi fúnra mi wà ní bèbè odò ńlá náà, èyíinì ni Hídẹ́kẹ́lì, mo sì ń bá a lọ láti gbé ojú mi sókè pẹ̀lú, mo sì rí, sì kíyè sí i, ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, ó sì fi wúrà Úfásì di ìgbáròkó rẹ̀ ní àmùrè.” (Dáníẹ́lì 10:4, 5) Hídẹ́kẹ́lì jẹ́ ọ̀kan lára odò mẹ́rin tí ó ṣàn wá láti inú ọgbà Édẹ́nì. (Jẹ́nẹ́sísì 2:10-14) Ní Páṣíà Àtijọ́, ohun tí a mọ Hídẹ́kẹ́lì sí ni Tigra, inú rẹ̀ ni orúkọ náà Tigris ní èdè Gíríìkì ti wá. Àgbègbè tí ó wà láàárín odò náà àti odò Yúfírétì ni a wá ń pè ní Mesopotámíà, tí ó túmọ̀ sí “Ilẹ̀ Tí Ó Wà Láàárín Àwọn Omi.” Èyí jẹ́rìí sí i pé ilẹ̀ Bábílónì ni Dáníẹ́lì ṣì wà nígbà tí ó rí ìran yìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó má jẹ́ inú ìlú Bábílónì ni ó wà.
-
-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
12, 13. Kí ni (a) aṣọ ońṣẹ́ náà fi hàn nípa ẹni tí ó jẹ́? (b) ìrísí ońṣẹ́ náà fi hàn nípa ẹni tí ó jẹ́?
12 Ẹ jẹ́ kí a túbọ̀ kíyè sí ońṣẹ́ àrà ọ̀tọ̀ yìí tí ó mú kí jìnnìjìnnì bo Dáníẹ́lì tó bẹ́ẹ̀. “Ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, ó sì fi wúrà Úfásì di ìgbáròkó rẹ̀ ní àmùrè.” Ní Ísírẹ́lì ìgbàanì, ọ̀gbọ̀ àtàtà lílọ́ tí a fi wúrà ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ ni a fi ń ṣe àmùrè, éfódì, àti ìgbàyà olórí àlùfáà àti aṣọ àwọn àlùfáà yòókù. (Ẹ́kísódù 28:4-8; 39:27-29) Nípa bẹ́ẹ̀, ìmúra ońṣẹ́ náà fi hàn pé ó jẹ́ mímọ́ àti pé ipò ńlá ni ó wà.
13 Ìrísí ońṣẹ́ náà tún ba Dáníẹ́lì lẹ́rù, ìyẹn ni bí ara rẹ̀ tí ó rí bí òkúta iyebíye ṣe ń tàn yinrin yinrin, ìrànyòò ojú rẹ̀ dídán tí ó lè múni lójú, bí ìbẹ́ṣẹ̀ṣẹ̀ ẹyinjú rẹ̀ tí ó rí bí iná ṣe ń wọni lára, àti bí apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ alágbára ṣe ń dán gbinrin. Kódà ìró ohùn rẹ̀ alágbára ń kó jìnnìjìnnì báni. Gbogbo èyí fi hàn dájúdájú pé kì í ṣe ènìyàn ẹlẹ́ran ara lásán. Áńgẹ́lì onípò gíga kan, tí ó ń sìn ní ibi mímọ́ níwájú Jèhófà, ni ẹni tí “ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀” yìí ní láti jẹ́, kò lè jẹ́ ẹlòmíràn, ibẹ̀ ni ó sì ti mú ìsọfúnni kan wá.a
-
-
Ońṣẹ́ kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún un LókunKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
a Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò dárúkọ áńgẹ́lì yìí, ó dà bí pé òun kan náà ni ẹni tí a gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ó ń sọ fún Gébúrẹ́lì pé kí ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ nípa ìran tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ rí nígbà yẹn. (Fi Dáníẹ́lì 8:2, 15, 16 wé Da 12:7, 8.) Síwájú sí i, Dáníẹ́lì 10:13 fi hàn pé Máíkẹ́lì, “ọ̀kan nínú àwọn ọmọ aládé tí ó wà ní ipò iwájú pátápátá,” wá ran áńgẹ́lì yìí lọ́wọ́. Nípa báyìí, áńgẹ́lì tí a kò dárúkọ rẹ̀ yìí ti ní àǹfààní láti bá Gébúrẹ́lì àti Máíkẹ́lì ṣiṣẹ́ pọ̀ tímọ́tímọ́.
-