-
Báwo Ni Àkókò Tó Ṣẹ́ Kù Fún Àwọn Olubi Ti Pọ̀ Tó?Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
-
-
9 Hábákúkù fetí sílẹ̀ dáadáa sí àwọn ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run tún bá a sọ, èyí tó wà nínú Hábákúkù orí kìíní, ẹsẹ ìkẹfà sí ìkọkànlá. Iṣẹ́ tí Jèhófà rán an nìyí, kò sì sí ọlọ́run èké kankan tàbí òkú òrìṣàkórìṣà tó lè ní kó má ṣẹ: “Èmi yóò gbé àwọn ará Kálídíà dìde, orílẹ̀-èdè tí ó korò, tí ó sì ní inú fùfù, èyí tí ń lọ sí àwọn ibi fífẹ̀ gbayawu ilẹ̀ ayé kí ó bàa lè gba àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tirẹ̀. Ó jẹ́ adajìnnìjìnnì-boni àti amúnikún-fún-ẹ̀rù. Láti ọ̀dọ̀ òun fúnra rẹ̀ ni ìdájọ́ òdodo tirẹ̀ àti iyì tirẹ̀ ti ń jáde lọ. Àwọn ẹṣin rẹ̀ sì jẹ́ èyí tí ó yára ju àmọ̀tẹ́kùn, wọ́n sì jẹ́ òǹrorò ju ìkookò ìrọ̀lẹ́. Àwọn ẹṣin ogun rẹ̀ sì ti fi àtẹ́sẹ̀ talẹ̀, ibi jíjìnnàréré sì ni àwọn ẹṣin ogun rẹ̀ ti wá. Wọ́n ń fò bí idì tí ń yára kánkán lọ jẹ nǹkan. Látòkè délẹ̀, kìkì ìwà ipá ni ó wá fún. Ìpéjọ ojú wọ́n dà bí ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn, ó sì ń kó àwọn òǹdè jọpọ̀ bí iyanrìn. Ní tirẹ̀, ó ń fi àwọn ọba pàápàá ṣe yẹ̀yẹ́, àwọn onípò àṣẹ gíga-gíga sì jẹ́ ohun apanilẹ́rìn-ín fún un. Ní tirẹ̀, ó ń fi gbogbo ibi olódi pàápàá rẹ́rìn-ín, ó sì ń kó ekuru jọ pelemọ, ó sì ń gbà á. Ní àkókò yẹn, dájúdájú, òun yóò lọ síwájú bí ẹ̀fúùfù, yóò sì kọjá lọ, yóò sì jẹ̀bi ní ti tòótọ́. Agbára rẹ̀ yìí wá láti ọwọ́ ọlọ́run rẹ̀.”
-
-
Báwo Ni Àkókò Tó Ṣẹ́ Kù Fún Àwọn Olubi Ti Pọ̀ Tó?Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
-
-
11. Báwo ni o ṣe lè ṣàpèjúwe bí àwọn ọmọ ogun Bábílónì ṣe kọlu Júdà?
11 Ẹṣin àwọn ará Bábílónì lè sáré ju àwọn àmọ̀tẹ́kùn eléré àsápajúdé lọ. Àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ rorò ju àwọn ìkookò arebipa, tí ń ṣọdẹ lóru. Bí wọ́n ti ń hára gàgà láti lọ, ‘àwọn ẹṣin ogun rẹ̀ fi àtẹ́sẹ̀ talẹ̀’ kùràkùrà. Láti iyàn-níyàn Bábílónì ni wọ́n ti forí lé Júdà. Bí idì tó ń fò bọ̀ láti wá ki oúnjẹ tó fẹ́ràn mọ́lẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Kálídíà yóò ṣe ki ẹran ọdẹ wọn mọ́lẹ̀ láìpẹ́. Ṣé àwọn ọmọ ogun díẹ̀ ló kàn ń gbé sùnmọ̀mí bọ̀ ni, tí wọ́n kàn fẹ́ wá kẹ́rù lọ? Rárá o! “Látòkè délẹ̀, kìkì ìwà ipá ni ó wá fún,” bí ọ̀pọ̀ yanturu ọmọ ogun tó rọ́ wá láti wá ṣeni bí ọṣẹ́ ti ń ṣojú. Híhá tí wọ́n ń hára gàgà mú kí wọ́n ranjú kankan, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gẹṣin lọ sí ìwọ̀ oòrùn Júdà àti Jerúsálẹ́mù, tí wọ́n sì ń sáré tete bí ẹ̀fúùfù ìlà oòrùn. Àwọn èèyàn tí àwọn ọmọ ogun Bábílónì kó lẹ́rú pọ̀ débi pé ṣe ni wọ́n ‘ń kó àwọn òǹdè bí iyanrìn.’
-