-
“Ẹ Dúró Dè Mí”Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | March 1
-
-
13. Ìhìn iṣẹ́ ìdájọ́ wo ni Sefaniah kéde lòdì sí Moabu, Ammoni, àti Assiria?
13 Nípasẹ̀ wòlíì rẹ̀ Sefaniah, Jehofa tún fi ìbínú rẹ̀ hàn sí àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fìyà jẹ àwọn ènìyàn rẹ̀. Ó polongo pé: “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn ọmọ Ammoni, nípa èyí tí wọn ti kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn. Nítorí náà bí èmi ti wà, ni Oluwa àwọn ọmọ ogun wí, Ọlọrun Israeli, Dájúdájú Moabu yóò dà bíi Sodomu, àti àwọn ọmọ Ammoni bíi Gomorra, bíi títàn wèrèpè, àti bí ihò iyọ̀, àti ìdahoro títí láé . . . Òun óò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí ìhà àríwá, yóò sì pa Assiria run; yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.”—Sefaniah 2:8, 9, 13.
14. Ẹ̀rí wo ní ó wà pé, àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì “gbé ara wọn ga” sí àwọn ọmọ Israeli àti Ọlọrun wọn, Jehofa?
14 Moabu àti Ammoni ti jẹ́ ọ̀tá Israeli tipẹ́tipẹ́. (Fi wé Onidajọ 3:12-14.) Òkúta Moabu, tí ó wà ní Ilé Ohun Ìṣẹ̀m̀báyé ti Louvre ní Paris, ní àkọlé kan tí ó ní ọ̀rọ̀ ìfọ́nnu tí Ọba Meṣa ará Moabu sọ nínú. Ó fi ìgbéraga sọ bí òún ṣe ṣẹ́gun àwọn ìlú ńlá Israeli mélòó kan pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ ọlọrun rẹ̀ Kemoṣi. (2 Awọn Ọba 1:1) Jeremiah, alájọgbáyé Sefaniah, sọ̀rọ̀ nípa bí àwọn ará Ammoni ṣe gba ilẹ̀ àwọn ọmọ Israeli ti Gadi ní orúkọ Malkomu ọlọrun wọn. (Jeremiah 49:1) Ní ti Assiria, Ọba Ṣalamaneseri Karùn-ún ti dó ti Samaria, ó sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ ní nǹkan bí ọ̀rúndún kan ṣáájú ọjọ́ Sefaniah. (2 Awọn Ọba 17:1-6) Kó pẹ́ púpọ̀ lẹ́yìn náà, Ọba Sennakaribi kọlu Juda, ó ṣẹ́gun púpọ̀ nínú àwọn ìlú ńlá olódi rẹ̀, àní ó tilẹ̀ halẹ̀ mọ́ Jerusalemu. (Isaiah 36:1, 2) Ní tòótọ́, agbẹnusọ fún ọba Assiria gbéra ga sí Jehofa nígbà tí ó ń fi dandan gbọ̀n béèrè pé kí Jerusalemu túúbá.—Isaiah 36:4-20.
-
-
“Ẹ Dúró Dè Mí”Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | March 1
-
-
15. Báwo ni Jehofa yóò ṣe tẹ́ àwọn ọlọrun àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti gbéra ga sí àwọn ènìyàn rẹ̀ lógo?
15 Orin Dafidi 83 mẹ́nu kan àwọn orílẹ̀-èdè mélòó kan, tí ó ní Moabu, Ammoni, àti Assiria nínú, tí ó gbéraga sí Israeli, tí ó sì fi tìhàlẹ̀tìhàlẹ̀ sọ pé: “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a ké wọn kúrò láti máa wà ní orílẹ̀-èdè; kí orúkọ Israeli kí ó má ṣe sí ní ìrántí mọ́.” (Orin Dafidi 83:4) Wòlíì náà Sefaniah fi tìgboyàtìgboyà kéde pé, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ọlọ́kàn gíga wọ̀nyí àti àwọn ọlọrun wọn ni Jehofa àwọn ọmọ ogun yóò tẹ́ lógo. “Èyí ni wọn óò ní nítorí ìgbéraga wọn, nítorí pé wọ́n ti kẹ́gàn, wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí ènìyàn Oluwa àwọn ọmọ ogun. Oluwa yoo jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn: nítorí òun óò mú kí gbogbo òrìṣà ilẹ̀ ayé kí ó rù; ènìyàn yóò sì máà sìn ín, olúkúlùkù láti ipò rẹ̀ wá, àní gbogbo erékùṣù àwọn kèfèrí.”—Sefaniah 2:10, 11.
-
-
“Ẹ Dúró Dè Mí”Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | March 1
-
-
18. (a) Báwo ni a ṣe mú ìdájọ́ àtọ̀runwá ṣẹ sórí Jerusalemu, èé sì ti ṣe? (b) Báwo ni a ṣe mú àsọtẹ́lẹ̀ Sefaniah nípa Moabu àti Ammoni ṣẹ?
18 Ọ̀pọ̀ àwọn Júù tí wọ́n dúró de Jehofa tún fojú rí bí a ṣe mú ìdájọ́ rẹ̀ ṣẹ sórí Juda àti Jerusalemu. Nípa Jerusalemu, Sefaniah ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé: “Ègbé ni fún ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́, fún ìlú aninilára nì. Òun kò fetí sí ohùn náà; òun kò gba ẹ̀kọ́; òun kò gbẹ́kẹ̀ lé Oluwa; òun kò sún mọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọrun rẹ̀.” (Sefaniah 3:1, 2) Nítorí àìṣòótọ́ rẹ̀, ìgbà méjì ni àwọn ará Babiloni dó ti Jerusalemu, nígbẹ́yìngbẹ́yín, wọ́n ṣẹ́gun rẹ̀, wọ́n sì pa á run ní ọdún 607 ṣáájú Sànmánì Tiwa. (2 Kronika 36:5, 6, 11-21) Ní ti Moabu àti Ammoni, gẹ́gẹ́ bí òpìtàn Júù nì, Josephus, ti sọ, ní ọdún karùn-ún, lẹ́yìn ìṣubú Jerusalemu, àwọn ará Babiloni gbé ogun dìde sí wọn, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Àṣẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀ wọ́n di àwátì, gẹ́gẹ́ bí a ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀.
-