-
Bí Àwọn Ìran Tí Sekaráyà Rí Ṣe Kàn Ẹ́Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017 | October
-
-
16. (a) Kí ló ṣẹlẹ̀ sí apẹ̀rẹ̀ òṣùwọ̀n eéfà tí Sekaráyà rí? (Wo àwòrán kẹta tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí.) (b) Ibo làwọn obìnrin tó ní ìyẹ́ lápá yẹn gbé apẹ̀rẹ̀ náà lọ?
16 Lẹ́yìn náà, Sekaráyà wá rí àwọn obìnrin méjì tí wọ́n ní ìyẹ́ apá bíi ti ẹyẹ àkọ̀. (Ka Sekaráyà 5:9-11.) Àwọn obìnrin yìí yàtọ̀ pátápátá sí obìnrin inú apẹ̀rẹ̀ yẹn. Àwọn obìnrin yìí fò lọ síbi tí apẹ̀rẹ̀ náà wà, wọ́n sì gbé apẹ̀rẹ̀ tí “Ìwà Burúkú” wà nínú rẹ̀. Ibo ni wọ́n ń gbé e lọ? “Ilẹ̀ Ṣínárì” tàbí Bábílónì ni wọ́n gbé e lọ. Àmọ́, kí nìdí tí wọ́n fi gbé apẹ̀rẹ̀ náà lọ sí Bábílónì?
17, 18. (a) Kí nìdí tó fi jẹ́ pé ilẹ̀ Ṣínárì ló tọ́ kí “Ìwà Burúkú” máa gbé? (b) Kí ló yẹ ká pinnu tó bá kan ọ̀rọ̀ ìwà burúkú?
17 Lásìkò tí Sekaráyà gbáyé, ilẹ̀ Ṣínárì ló tọ́ kí Ìwà Burúkú máa gbé. Sekaráyà àtàwọn Júù bíi tiẹ̀ náà mọ̀ dáadáa pé ojúkò ìwà burúkú ni ìlú Bábílónì jẹ́ nígbà yẹn lọ́hùn-ún. Ó ṣe tán, ibẹ̀ lọ̀pọ̀ wọn dàgbà sí, ìyẹn láàárín àwọn èèyàn tó ń bọ òrìṣà, tí ìwà búburú sì kún ọwọ́ wọn. Kódà, ojoojúmọ́ làwọn Júù yẹn ń sapá káwọn èèyàn náà má bàa kó èèràn ràn wọ́n. Ẹ wo bí ìran yẹn ṣe máa múnú wọn dùn tó! Jèhófà mú kó dá wọn lójú pé kò sí ohunkóhun tó máa ba ìjọsìn mímọ́ òun jẹ́!
18 Bó ti wù kó rí, ìran yẹn náà tún jẹ́ káwọn Júù mọ̀ pé wọ́n gbọ́dọ̀ rí i dájú pé ohunkóhun kò ba ìjọsìn mímọ́ wọn jẹ́. Ìwà burúkú èyíkéyìí kò gbọ́dọ̀ wáyé láàárín àwọn èèyàn Ọlọ́run, tó bá sì wáyé, wọn ò gbọ́dọ̀ fàyè gbà á. Ní báyìí táwa náà wà nínú ètò Jèhófà, tá a sì ń gbádùn ààbò àti ìfẹ́ rẹ̀, a ò gbọ́dọ̀ fàyè gba ẹ̀gbin èyíkéyìí nínú ètò náà. Ṣé à ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti jẹ́ kí ilé Jèhófà wà ní mímọ́? Kò sáyè fún ìwà burúkú èyíkéyìí nínú Párádísè tẹ̀mí tá a wà yìí.
-