-
Jèhófà Kórìíra Ìwà ÀdàkàdekèIlé Ìṣọ́—2002 | May 1
-
-
5, 6. (a) Èé ṣe tó fi jẹ́ pé àwọn àlùfáà wọ̀nyẹn gan-an ni ìbáwí tọ́ sí? (b) Báwo ni Jèhófà ṣe fi hàn pé ojú ẹni àbùkù lòun fi ń wo àwọn àlùfáà wọ̀nyẹn?
5 Èé ṣe tó fi jẹ́ pé àwọn àlùfáà wọ̀nyẹn gan-an ni ìbáwí tọ́ sí? Ẹsẹ keje sọ ìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀, ó ní: “Ètè àlùfáà ni èyí tí ó yẹ kí ó pa ìmọ̀ mọ́, òfin sì ni ohun tí ó yẹ kí àwọn ènìyàn máa wá ní ẹnu rẹ̀; nítorí pé òun ni ońṣẹ́ Jèhófà àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun.” Ní ohun tó lé ní ẹgbẹ̀rún ọdún ṣáájú àkókò yẹn, òfin Ọlọ́run tá a fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípasẹ̀ Mósè sọ pé iṣẹ́ àwọn àlùfáà ni “láti kọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní gbogbo ìlànà tí Jèhófà ti sọ.” (Léfítíkù 10:11) Ó ṣeni láàánú pé, bí ọdún ti ń gorí ọdún, ẹni tó kọ 2 Kíróníkà 15:3 ròyìn pé: “Ọjọ́ púpọ̀ sì ni Ísírẹ́lì fi wà láìní Ọlọ́run tòótọ́ àti láìní àlùfáà tí ń kọ́ni àti láìní Òfin.”
6 Ipò kan náà làwọn àlùfáà wà nígbà ayé Málákì, ní ọ̀rúndún kárùn-ún ṣááju Sànmánì Tiwa. Wọ́n ń kùnà láti fi Òfin Ọlọ́run kọ́ àwọn èèyàn náà. Nítorí náà, ìbáwí tọ́ sí àwọn àlùfáà wọ̀nyẹn. Kíyè sí ọ̀rọ̀ líle tí Jèhófà sọ sí wọn. Málákì 2:3 là á mọ́lẹ̀ pé: “Èmi yóò sì fọ́n imí sójú yín, imí àwọn àjọyọ̀ yín.” Ìbáwí ńlá mà lèyí o! Òde ibùdó ló yẹ kí wọ́n kó imí àwọn ẹran tá a fi rúbọ lọ, kí wọ́n sì lọ sun wọ́n níbẹ̀. (Léfítíkù 16:27) Àmọ́, nígbà tí Jèhófà sọ fún wọn pé ojú wọn lòun máa fọ́n ìmí náà sí, ó hàn gbangba pé ojú àbùkù ló fi ń wo àti ẹbọ àtàwọn tó ń rú wọn.
-
-
Jèhófà Kórìíra Ìwà ÀdàkàdekèIlé Ìṣọ́—2002 | May 1
-
-
11. Àwọn wo ló yẹ kó máa ṣọ́ra jù?
11 Ní ti àwọn tó láǹfààní kíkọ́ni ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run nínú ìjọ lónìí, Málákì 2:7 gbọ́dọ̀ jẹ́ ìkìlọ̀ ńlá fún wọn. Ó sọ pé ètè wọn “ni èyí tí ó yẹ kí ó pa ìmọ̀ mọ́, òfin sì ni ohun tí ó yẹ kí àwọn ènìyàn máa wá” ní ẹnu wọn. Ẹrù iṣẹ́ ńlá ló já lé irú àwọn olùkọ́ bẹ́ẹ̀ léjìká, nítorí pé Jákọ́bù 3:1 là á mọ́lẹ̀ pé àwọn ni “yóò gba ìdájọ́ tí ó wúwo jù.” Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbọ́dọ̀ fi tokuntokun àti tìtaratìtara kọ́ni, síbẹ̀ ẹ̀kọ́ wọn gbọ́dọ̀ jẹ́ èyí tá a gbé ka ìwé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àtàwọn ìtọ́ni tó ń wá nípasẹ̀ ètò àjọ Jèhófà. Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n á “tóótun tẹ́rùntẹ́rùn láti kọ́ àwọn ẹlòmíràn.” Ìdí nìyẹn tá a fi gbà wọ́n nímọ̀ràn pé: “Sa gbogbo ipá rẹ láti fi ara rẹ hàn fún Ọlọ́run ní ẹni tí a tẹ́wọ́ gbà, aṣiṣẹ́ tí kò ní ohun kankan láti tì í lójú, tí ń fi ọwọ́ títọ̀nà mú ọ̀rọ̀ òtítọ́.”—2 Tímótì 2:2, 15.
12. Kí ló yẹ kí àwọn tó jẹ́ olùkọ́ni ṣọ́ra fún?
12 Bí a kò bá ṣọ́ra, ó lè ṣe wá bíi pé ká fi àwọn ọ̀rọ̀ tara wa tàbí àwọn èrò tiwa kún ẹ̀kọ́ wa nígbà mìíràn. Ìyẹn lè jẹ́ ewu ńlá, àgàgà fún ẹnì kan tó máa ń fẹ́ kó jẹ́ pé ohun tí òun bá sọ labẹ́ gé, kódà bí ohun tó ń sọ tiẹ̀ lòdì sí ẹ̀kọ́ tí ètò àjọ Jèhófà fi ń kọ́ni. Àmọ́ Málákì orí kejì fi hàn pé ó yẹ kí ọkàn wa balẹ̀ pé àwọn olùkọ́ nínú ìjọ yóò tẹ̀ lé ìmọ̀ tó wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run, kì í ṣe èrò ti ara wọn tó lè mú àwọn àgùntàn kọsẹ̀. Jésù sọ pé: “Ẹnì yòówù tí ó bá mú ọ̀kan nínú àwọn ẹni kékeré wọ̀nyí tí wọ́n ní ìgbàgbọ́ nínú mi kọsẹ̀, ó ṣàǹfààní púpọ̀ fún un kí a so ọlọ kọ́ ọrùn rẹ̀, irúfẹ́ èyí tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ máa ń yí, kí a sì rì í sínú òkun gbalasa, tí ó lọ salalu.”—Mátíù 18:6.
-