-
Àwọn Àpèjúwe Nípa Ìjọba Ọlọ́runJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Jésù tún sọ àpèjúwe mẹ́ta míì fáwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀. Lákọ̀ọ́kọ́, ó sọ pé: “Ìjọba ọ̀run dà bí ìṣúra tí a fi pa mọ́ sínú pápá, èyí tí ọkùnrin kan rí, tó sì fi pa mọ́; torí pé inú rẹ̀ ń dùn, ó lọ ta gbogbo ohun tó ní, ó sì ra pápá yẹn.”—Mátíù 13:44.
-
-
Àwọn Àpèjúwe Nípa Ìjọba Ọlọ́runJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Nínú àpèjúwe méjèèjì yìí, Jésù tẹnu mọ́ ọn pé èèyàn gbọ́dọ̀ múra tán láti yááfì àwọn nǹkan kan kó lè rí ohun tó ṣeyebíye. Ọkùnrin oníṣòwò inú àpèjúwe yẹn tètè ta “gbogbo ohun tó ní” kó lè ra péálì tó níye lórí gan-an. Ó dájú pé àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù máa lóye àpèjúwe péálì tó ṣeyebíye náà dáadáa. Bákan náà, ọkùnrin tó rí ìṣúra tí a fi pa mọ́ sínú pápá “ta gbogbo ohun” tó ní kó lè rà á. Nínú àpèjúwe méjèèjì, ohun tó ṣeyebíye làwọn méjèèjì fẹ́ rà, kí wọ́n sì tọ́jú. A lè fi wé àwọn nǹkan téèyàn ń yááfì kó lè wá ìtọ́sọ́nà Ọlọ́run. (Mátíù 5:3) Àwọn kan lára àwọn tó ń fetí sí àpèjúwe yìí ti yááfì ọ̀pọ̀ nǹkan kí wọ́n lè máa wá ìtọ́sọ́nà Ọlọ́run, kí wọ́n sì di ọmọ ẹ̀yìn Jésù.—Mátíù 4:19, 20; 19:27.
-