-
Ẹ Mú Ìfòyebánilò DàgbàIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 1
-
-
Ìṣeétẹ̀síhìn-ín-sọ́hùn-ún Lójú Àwọn Àyíká-Ipò tí Ń Yípadà
6. Báwo ni Jesu ṣe fi ìfòyebánilò hàn nípa ọwọ́ tí ó fi mú obìnrin Keferi náà tí ẹ̀mí-èṣù ń dá ọmọbìnrin rẹ̀ lóró?
6 Bíi ti Jehofa, Jesu fi ara rẹ̀ hàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ń yára láti yí ìgbésẹ̀ padà tàbí mú ara rẹ̀ bá àwọn ipò titun mu bí wọ́n ti ń dìde. Ní àkókò kan obìnrin Keferi kan bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wo ọmọbìnrin òun tí ẹ̀mí-èṣù ń dálóró gidigidi sàn. Ní àwọn ọ̀nà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, Jesu kọ́kọ́ fihàn pé òun kò ní ràn án lọ́wọ́—àkọ́kọ́, nípa kíkọ̀ láti dá a lóhùn; èkejì, nípa sísọ ní tààràtà pé a rán òun sí àwọn Ju, kìí ṣe sí àwọn Kèfèrí; àti ẹ̀kẹta, nípa ṣíṣe àkàwé kan tí ó sọ kókó kan náà lọ́nà tí ó fi inúrere hàn. Ṣùgbọ́n, obìnrin náà tẹpẹlẹ mọ́ ọn jálẹ̀ gbogbo èyí, ní fífúnni ní ẹ̀rí ìgbàgbọ́ àrà-ọ̀tọ̀. Ní gbígbé ti àyíká ipò àrà-ọ̀tọ̀ yìí yẹ̀wò, Jesu lè rí i pé èyí kìí ṣe àkókò láti fipá mú ìlànà gbogbogbòò kan ṣẹ; ó jẹ́ àkókò láti tẹ̀ síhà kan ní ìdáhùn sí àwọn ìlànà gíga jù.a Nípa báyìí, Jesu ṣe ohun náà gan-an tí ó ti fihàn ní ìgbà mẹ́ta pé òun kò ní ṣe. Ó wo ọmọbìnrin obìnrin náà sàn!—Matteu 15:21-28.
-
-
Ẹ Mú Ìfòyebánilò DàgbàIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 1
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]
Nígbà tí obìnrin kan fi ìgbàgbọ́ àrà-ọ̀tọ̀ hàn, Jesu rí i pé èyí kìí ṣe àkókò láti fipá mú ìlànà gbogbogbòò kan ṣẹ
-