-
Kí a Gbé Ìjọ RóIlé Ìṣọ́—2007 | April 15
-
-
10. Báwo ni Mátíù 18:15-17 ṣe sọ pé káwọn Kristẹni yanjú ìṣòro ńlá tó bá wà láàárín wọn?
10 Jésù náà fi hàn pé ètò níní alábòójútó nínú ìjọ yóò wà. Rántí ọ̀rọ̀ tó wà nínú Mátíù 18:15-17, níbi tí Jésù ti sọ pé, nígbà míì, ìṣòro lè wáyé láàárín ẹni méjì tó jẹ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run, nígbà tí ọ̀kan bá ṣẹ ìkejì. Jésù sọ pé kí ẹni tí wọ́n ṣẹ̀ lọ bá ẹnì kejì láti “fi àléébù rẹ̀ hàn án,” ìyẹn ni pé kó lọ sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un láìmú ẹlòmíì dání. Ó ní tí ìgbésẹ̀ yẹn ò bá yanjú ìṣòro ọ̀hún, kí ó pe ẹnì kan tàbí ẹni méjì tó mọ̀ nípa ọ̀ràn náà láti bá wọn dá sí i. Àmọ́ tó bá jẹ́ pé ibi pẹlẹbẹ kan náà ni ọ̀bẹ fi ń lélẹ̀ ńkọ́? Jésù sọ pé: “Bí kò bá fetí sí wọn, sọ fún ìjọ. Bí kò bá fetí sí ìjọ pàápàá, jẹ́ kí ó rí sí ọ gan-an gẹ́gẹ́ bí ènìyàn àwọn orílẹ̀-èdè àti gẹ́gẹ́ bí agbowó orí.” Láyé ìgbà tí Jésù sọ ọ̀rọ̀ yẹn, àwọn Júù ṣì ni “ìjọ Ọlọ́run,” ìyẹn ló fi jẹ́ pé àwọn ni ọ̀rọ̀ náà ń bá wí.a Ṣùgbọ́n nígbà tá a dá ìjọ Kristẹni sílẹ̀ lẹ́yìn náà, àwọn tó wà nínú ìjọ náà ni ọ̀rọ̀ náà wá ń bá wí. Èyí jẹ́ ohun mìíràn tó fi hàn pé àwọn èèyàn Ọlọ́run yóò ní ìjọ tá a ṣètò níbi tá ò ti máa gbé olúkúlùkù wọn ró tí wọ́n á sì ti máa gba ìtọ́sọ́nà.
11. Ipa wo làwọn alàgbà ń kó nínú yíyanjú ìṣòro?
11 Ó bá a mu pé àwọn àgbà ọkùnrin tàbí àwọn alábòójútó ni yóò máa ṣojú fún ìjọ láti bójú tó ọ̀ràn tó bá jẹ yọ láàárín àwọn ará àtèyí tó jẹ mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ dídá. Èyí wà lára ohun tí Títù 1:9 sọ pé àwọn tó bá máa di alàgbà gbọ́dọ̀ kúnjú ìwọ̀n rẹ̀. Lóòótọ́, àwọn alàgbà ìjọ wọ̀nyẹn kì í ṣe ẹni pípé bí Títù tí Pọ́ọ̀lù rán pé kó lọ sí àwọn ìjọ láti lọ “ṣe àtúnṣe àwọn ohun tí ó ní àbùkù” kì í ti í ṣe ẹni pípé. (Títù 1:4, 5) Lóde òní, kí wọ́n tó yan ẹnì kan gẹ́gẹ́ bí alàgbà, onítọ̀hún ní láti jẹ́ ẹni tí ìwà rẹ̀ ti fi hàn látìgbà pípẹ́ pé ó jẹ́ onígbàgbọ́ àti olùfọkànsìn. Ìyẹn ló máa jẹ́ káwọn ará yòókù nínú ìjọ lè fọkàn tán ìtọ́sọ́nà àti ìdarí táwọn alàgbà bá ń fún wọn.
-
-
Kí a Gbé Ìjọ RóIlé Ìṣọ́—2007 | April 15
-
-
a Ọ̀mọ̀wé kan tó ń jẹ́ Albert Barnes tó kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ nípa Bíbélì gbà pé nígbà tí Jésù fún àwọn Kristẹni nítọ̀ọ́ni pé kí wọ́n “sọ fún ìjọ,” ìjọ tó sọ yìí lè túmọ̀ sí “àwọn tí wọ́n láṣẹ láti gbọ́ irú ẹjọ́ bẹ́ẹ̀, ìyẹn àwọn tó ń ṣojú fún ìjọ. Nínú sínágọ́gù àwọn Júù, àwọn alàgbà kan wà tí wọ́n jẹ́ onídàájọ́. Àwọn ni wọ́n máa ń gbọ́ irú ẹjọ́ bẹ́ẹ̀.”
-