-
“Àánú Ṣe É”“Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
3 Pẹ̀lú bí ariwo ogunlọ́gọ̀ náà ṣe ròkè tó, Jésù ṣì gbọ́ igbe àwọn alágbe náà. Kí ló máa ṣe o? Ọ̀pọ̀ nǹkan ló gbé sọ́kàn. Nǹkan bí ọ̀sẹ̀ kan péré ló kù kó lò láyé. Ó mọ̀ pé dẹndẹ ìyà àti ikú oró ń dúró de òun ní Jerúsálẹ́mù. Síbẹ̀ kò tìtorí ìyẹn fi gbígbọ́ ṣaláìgbọ́ bí àwọn alágbe yẹn ò ṣe yéé bẹ̀ ẹ́. Ó tẹsẹ̀ dúró díẹ̀, ó wá ní kí wọ́n mú àwọn alágbe tó ń kígbe yẹn sún mọ́ òun. Àwọn alágbe náà bẹ̀bẹ̀ pé: “Olúwa, jẹ́ kí ojú wa là.” “Bí àánú ti ṣe é,” ó fọwọ́ kan ojú wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ríran.a Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ̀ lé Jésù.—Lúùkù 18:35-43; Mátíù 20:29-34.
-
-
“Àánú Ṣe É”“Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
a Wọ́n ní ọ̀kan lára àwọn ọ̀rọ̀ Gíríìkì tó tíì dáa jù láti fi ṣàpèjúwe ìyọ́nú ni ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n túmọ̀ sì ‘àánú ṣe é.’ Ìwé kan sọ pé “kì í ṣe pé kéèyàn rí ìyà tó ń jẹ ọmọlàkejì kó sì dunni nìkan ni, ṣùgbọ́n ó ní nínú kéèyàn fẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tó bá lè ṣe láti gba onítọ̀hún sílẹ̀ lọ́wọ́ ìnira yẹn tàbí kéèyàn bá a fòpin sí ìyà náà.”
-