-
‘Kí Ni Yóò Ṣe Àmì Wíwàníhìn-Ín Rẹ?’Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | February 15
-
-
13. Èéṣe tí ó fi ṣeéṣe fún àwọn Kristian láti kọbiara sí ìkìlọ̀ Jesu láti sálọ?
13 Ṣùgbọ́n bí àwọn ará Romu bá fàsẹ́yìn kúrò ní àyíká Jerusalemu, èéṣe tí ẹnikẹ́ni fi níláti sálọ? Àwọn ọ̀rọ̀ Jesu fihàn pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ náà jẹ́ ẹ̀rí pé ‘ìsọdahoro Jerusalemu ti súnmọ́lé.’ (Luku 21:20, NW) Bẹ́ẹ̀ni, ìsọdahoro. Ó sàsọtẹ́lẹ̀ ‘ìpọ́njú irú èyí tí kò tíì wáyé rí láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ tí kì yóò sì tún wáyé mọ́.’ Ní nǹkan bí ọdún mẹ́ta àti ààbọ̀ lẹ́yìn náà, ní 70 C.E., Jerusalemu ní ìrírí “ìpọ́njú ńlá” náà níti gidi láti ọwọ́ ẹgbẹ́-ọmọ-ogun Romu lábẹ́ Ọ̀gágun Titus. (Matteu 24:21, NW; Marku 13:19) Ṣùgbọ́n, èéṣe tí Jesu fi ṣàpèjúwe èyí gẹ́gẹ́ bí ìpọ́njú tí ó tóbi ju èyíkéyìí tí ó tíì ṣẹlẹ̀ ṣáájú tàbí láti ìgbà náà wá?
14. Èéṣe tí a fi lè sọ pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí Jerusalemu ní 70 C.E. jẹ́ “ìpọ́njú ńlá” irú èyí tí kò tíì wáyé tàbí tí kò tíì ṣẹlẹ̀ láti ìgbà yìí wá?
14 Jerusalemu ni àwọn ará Babiloni run bàjẹ́ ní 607 B.C.E., ìlú-ńlá náà sì ti rí ìjà ẹlẹ́rùjẹ̀jẹ̀ nínú ọ̀rúndún wa yìí. Síbẹ̀, ohun tí ó wáyé ní 70 C.E. jẹ́ ìpọ́njú ńlá aláìlẹ́gbẹ́. Ní àkókò ogun tí ó gbà tó oṣù márùn-ún, àwọn jagunjagun Titus ṣẹ́gun àwọn Ju. Wọn pa nǹkan bíi 1,100,000 wọ́n sì kó iye tí ó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó 100,000 lẹ́rú. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, àwọn ará Romu wó Jerusalemu palẹ̀. Èyí fi ẹ̀rí hàn pé ètò-ìgbékalẹ̀ àwọn Ju tí a gbé ìjọsìn rẹ̀ tí ó ṣètẹ́wọ́gbà tẹ́lẹ̀ karí tẹ́ḿpìlì ti dópin títí gbére. (Heberu 1:2) Bẹ́ẹ̀ni, lọ́nà tí ó tọ̀nà àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ 70 C.E. ni a lè kà sí ‘ìpọ́njú irúfẹ́ èyí tí kò tíì wáyé [sórí ìlú-ǹlá, orílẹ̀-èdè, àti ètò-ìgbékalẹ̀ yẹn] rí láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé, rárá o, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò tún wáyé mọ́.’—Matteu 24:21, NW.d
-
-
‘Kí Ni Yóò Ṣe Àmì Wíwàníhìn-Ín Rẹ?’Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | February 15
-
-
d Òǹkọ̀wé ọmọ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì Matthew Henry ṣàlàyé pé: “Ìparun Jerusalemu láti ọwọ́ àwọn ara Kaldea banilẹ́rù gan-an, ṣùgbọ́n èyí rékọjá rẹ̀. Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ ìparẹ́ ráúráú gbogbo àwọn . . . Ju.”
-
-
‘Kí Ni Yóò Ṣe Àmì Wíwàníhìn-Ín Rẹ?’Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | February 15
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 10]
Ìpọ́njú 70 C.E. ni èyí tí ó tóbi jùlọ tí Jerusalemu àti ètò-ìgbékalẹ̀ àwọn Ju tíì ní ìrírí rẹ̀ rí
-