-
Ìwọ Ha Wà ní Sẹpẹ́ De Ọjọ́ Jèhófà Bí?Ilé Ìṣọ́—1997 | March 1
-
-
9. Àlàyé wo ni Jésù ṣe, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sílẹ̀ nínú Mátíù 24:36?
9 Iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba àti àwọn apá mìíràn nínú àmì wíwàníhìn-ín Jésù tí a sọ tẹ́lẹ̀ ti ń nímùúṣẹ lọ́wọ́lọ́wọ́. Nítorí náà, òpin kù sí dẹ̀dẹ̀ fún ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan ti ìsinsìnyí. Lóòótọ́, Jésù wí pé: “Ní ti ọjọ́ àti wákàtí yẹn kò sí ẹnì kan tí ó mọ̀, kì í ṣe àwọn áńgẹ́lì àwọn ọ̀run tàbí Ọmọkùnrin, bí kò ṣe Bàbá nìkan.” (Mátíù 24:4-14, 36) Ṣùgbọ́n, àsọtẹ́lẹ̀ Jésù lè ràn wá lọ́wọ́ láti wà ní sẹpẹ́ fún “ọjọ́ àti wákàtí yẹn.”
-
-
Ìwọ Ha Wà ní Sẹpẹ́ De Ọjọ́ Jèhófà Bí?Ilé Ìṣọ́—1997 | March 1
-
-
14. Kí ni Jèhófà sọ fún Nóà lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, èé sì ti ṣe?
14 Bí áàkì náà ti ń parí lọ, Nóà ti lè máa ronú pé Ìkún Omi náà ti sún mọ́lé, bí òun kò tilẹ̀ mọ ọjọ́ náà pàtó tí yóò ṣẹlẹ̀. Lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, Jèhófà sọ fún un pé: “Ní ọjọ́ méje sí i, èmi óò mú òjò rọ̀ sí ilẹ̀ ní ogójì ọ̀sán àti ní ogójì òru.” (Jẹ́nẹ́sísì 7:4) Ìyẹn fún Nóà àti ìdílé rẹ̀ ní àkókò tí ó tó láti mú gbogbo onírúurú ẹranko wá sínú áàkì náà, kí àwọn pẹ̀lú sì wọ inú rẹ̀ kí Ìkún Omi tó bẹ̀rẹ̀. Kò pọn dandan fún wa láti mọ ọjọ́ àti wákàtí náà fún ìbẹ̀rẹ̀ ìparun ètò ìgbékalẹ̀ yí; a kò fi lílà á já àwọn ẹranko lé wa lọ́wọ́, àwọn ẹ̀dá ènìyàn tí yóò sì ṣeé ṣe fún láti là á já ti ń wọnú áàkì ìṣàpẹẹrẹ náà nísinsìnyí, párádísè tẹ̀mí ti àwọn ènìyàn Ọlọ́run.
-