-
‘Ẹrú Olóòótọ́’ Náà Yege Nígbà Àbẹ̀wò!Ilé Ìṣọ́—2004 | March 1
-
-
2, 3. Ibo ni “ẹrú búburú yẹn” ti wá, báwo ló sì ṣe di ẹni burúkú?
2 Jésù sọ̀rọ̀ nípa ẹrú búburú náà kété lẹ́yìn tó sọ̀rọ̀ nípa “ẹrú olóòótọ́ àti olóye.” Ó sọ pé: “Bí ẹrú búburú yẹn bá lọ sọ nínú ọkàn-àyà rẹ̀ pẹ́nrẹ́n pé, ‘Ọ̀gá mi ń pẹ́,’ tí ó sì wá bẹ̀rẹ̀ sí lu àwọn ẹrú ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó sì ń jẹ, tí ó sì ń mu pẹ̀lú àwọn ọ̀mùtí paraku, ọ̀gá ẹrú yẹn yóò dé ní ọjọ́ tí kò fojú sọ́nà fún àti ní wákàtí tí kò mọ̀, yóò sì fi ìyà mímúná jù lọ jẹ ẹ́, yóò sì yan ipa tirẹ̀ fún un pẹ̀lú àwọn alágàbàgebè. Níbẹ̀ ni ẹkún rẹ̀ àti ìpayínkeke rẹ̀ yóò wà.” (Mátíù 24:48-51) Gbólóhùn náà “ẹrú búburú yẹn” pe àfiyèsí wa sí ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ ṣáájú nípa ẹrú olóòótọ́ àti olóye. Ó dájú pé “ẹrú búburú” náà jẹ́ ara ẹgbẹ́ ẹrú olóòótọ́ náà nígbà kan rí.a Báwo ló ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀?
-
-
‘Ẹrú Olóòótọ́’ Náà Yege Nígbà Àbẹ̀wò!Ilé Ìṣọ́—2004 | March 1
-
-
4. Kí ni Jésù ṣe fún “ẹrú búburú” náà àti fún gbogbo àwọn tó fi irú ẹ̀mí bíi ti ẹrú náà hàn?
4 Àwọn Kristẹni tẹ́lẹ̀ rí yìí la wá mọ̀ sí “ẹrú búburú” náà, Jésù sì “fi ìyà mímúná jù lọ jẹ” wọ́n. Báwo ló ṣe ṣe é? Ó kọ̀ wọ́n sílẹ̀, wọ́n sì pàdánù ìrètí wọn ti ọ̀run. Àmọ́ ṣá o, a kò pa wọn run lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Wọ́n kọ́kọ́ fara da sáà ẹkún àti ìpayínkeke nínú “òkùnkùn lóde” ìjọ Kristẹni. (Mátíù 8: 12) Láti àwọn ọjọ́ wọ̀nyẹn wa, àwọn ẹni àmì òróró mélòó kan ti fi irú ẹ̀mí búburú kan náà hàn, wọ́n sì sọ ara wọn di “ẹrú búburú.” Àwọn kan lára “àwọn àgùntàn mìíràn” fara wé ìwà àìṣòótọ́ wọn. (Jòhánù 10:16) Gbogbo irú àwọn ọ̀tá Kristi bẹ́ẹ̀ ló máa ń bá ara wọn nínú ‘òkùnkùn tẹ̀mí lóde.’
-