ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọjọ́ Ọ̀la Wo Ni Ó Wà Fún Àwọn Àgùntàn àti Ewúrẹ́?
    Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | October 15
    • 7, 8. Kí ni Jesu sọ nípa àwọn àgùntàn, nítorí náà, ìparí èrò wo ni a lè dé nípa wọn?

      7 A kà nípa ṣíṣèdájọ́ àwọn àgùntàn pé: “[Jesu] yoo wí fún awọn wọnnì tí wọ́n wà ní ọ̀tún rẹ̀ pé, ‘Ẹ wá, ẹ̀yin tí Baba mi ti bùkún, ẹ jogún ìjọba tí a ti pèsè sílẹ̀ fún yín lati ìgbà pípilẹ̀ ayé. Nitori ebi pa mí ẹ sì fún mi ní nǹkan lati jẹ; òùngbẹ gbẹ mí ẹ sì fún mi ní nǹkan lati mu. Mo jẹ́ àjèjì ẹ sì gbà mí pẹlu ẹ̀mí aájò àlejò; mo wà ní ìhòòhò, ẹ sì fi aṣọ wọ̀ mí. Mo dùbúlẹ̀ àìsàn ẹ sì bójútó mi. Mo wà ninu ẹ̀wọ̀n ẹ sì wá sọ́dọ̀ mi.’ Nígbà naa ni awọn olódodo yoo fi ọ̀rọ̀ wọnyi dá a lóhùn pé, ‘Oluwa, nígbà wo ni awa rí ọ tí ebi ń pa ọ́ tí a sì bọ́ ọ, tabi tí òùngbẹ ń gbẹ ọ́, tí a sì fún ọ ní nǹkan lati mu? Nígbà wo ni awa rí ọ ní àjèjì tí a sì gbà ọ́ pẹlu ẹ̀mí aájò àlejò, tabi tí o wà ní ìhòòhò, tí a sì fi aṣọ wọ̀ ọ́? Nígbà wo ni awa rí ọ tí o ń ṣàìsàn tabi tí o wà ninu ẹ̀wọ̀n tí a sì lọ sọ́dọ̀ rẹ?’ Ní ìfèsìpadà ọba yoo sì wí fún wọn pé, ‘Ní òótọ́ ni mo wí fún yín, Dé ìwọ̀n tí ẹ̀yin ti ṣe é fún ọ̀kan ninu awọn kíkéré jùlọ ninu awọn arákùnrin mi wọnyi, ẹ̀yin ti ṣe é fún mi.’”—Matteu 25:34-40.

  • Ọjọ́ Ọ̀la Wo Ni Ó Wà Fún Àwọn Àgùntàn àti Ewúrẹ́?
    Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | October 15
    • 10, 11. (a) Èé ṣe tí kò fi lọ́gbọ́n nínú láti rò pé àwọn àgùntàn náà ní gbogbo ẹni tí ń fi inú rere hàn sí àwọn arákùnrin Jesu nínú? (b) Ta ni àwọn àgùntàn náà ń ṣojú fún lọ́nà yíyẹ?

      10 Ṣe ohun tí Jesu ń sọ ni pé, gbogbo ẹni tí ó bá ṣáà ti fi inú rere díẹ̀ hàn sí ọ̀kan lára àwọn arákùnrin rẹ̀, irú bíi fífúnni ní ègé búrẹ́dì kan tàbí ife omi kan, ti tóótun gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn àgùntàn wọ̀nyí bí? Òtítọ́ ni pé, fífi irú inú rere bẹ́ẹ̀ hàn lè ṣàgbéyọ inú rere ẹ̀dá ènìyàn, ṣùgbọ́n ní ti gidi, ó dà bíi pé ohun púpọ̀ sí i wé mọ́ àwọn àgùntàn inú òwe àkàwé yìí. Fún àpẹẹrẹ, ó dájú ṣáká pé, kì í ṣe àwọn aláìgbọlọ́rungbọ́ tàbí àwùjọ àlùfáà tí wọ́n fi inú rere hàn sí ọ̀kan lára àwọn arákùnrin rẹ̀ ní Jesu ń tọ́ka sí. Kàkà bẹ́ẹ̀, ìgbà méjì ni Jesu pe àwọn àgùntàn ní “awọn olódodo.” (Matteu 25:37, 46) Nítorí náà, àwọn àgùntàn náà gbọ́dọ̀ jẹ́ àwọn kan tí wọ́n ti ṣèrànwọ́ jálẹ̀ sáà àkókò kan—nípa fífi taápọntaápọn ṣètìlẹ́yìn—fún àwọn arákùnrin Kristi, tí wọ́n sì ti lo ìgbàgbọ́ títí dé àyè rírí ìdúró òdodo gbà níwájú Ọlọrun.

      11 Jálẹ̀ àwọn ọ̀rúndún, ọ̀pọ̀ àwọn bí Abrahamu ti gbádùn ìdúró òdodo. (Jakọbu 2:21-23) Noa, Abrahamu, àti àwọn mìíràn tí wọ́n jẹ́ olùṣòtítọ́ wà lára “awọn àgùtàn mìíràn” tí yóò jogún ìyè nínú Paradise lábẹ́ Ìjọba Ọlọrun. Lẹ́nu àìpẹ́ yìí, àràádọ́ta ọ̀kẹ́ púpọ̀ sí i ti tẹ́wọ́ gba ìjọsìn tòótọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn àgùntàn mìíràn, wọ́n sì ti di “agbo kan” pẹ̀lú àwọn ẹni-àmì-òróró. (Johannu 10:16; Ìṣípayá 7:9) Àwọn wọ̀nyí, tí wọ́n ní ìrètí ti orí ilẹ̀ ayé mọ àwọn arákùnrin Jesu gẹ́gẹ́ bí àwọn aṣojú Ìjọba náà, wọ́n sì tìtoríi bẹ́ẹ̀ ràn wọ́n lọ́wọ́—nípa ti ara àti nípa tẹ̀mí. Jesu ka ohun tí àwọn àgùntàn mìíràn náà ti ṣe fún àwọn arákùnrin òun lórí ilẹ̀ ayé sí ohun tí wọ́n ṣe sí òun. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ tí wọ́n wà láàyè nígbà tí ó bà wá láti ṣèdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni a óò ṣèdájọ́ fún pé wọ́n jẹ́ àgùntàn.

      12. Èé ṣe tí àwọn àgùntàn náà fi lè béèrè bí wọ́n ti ṣe hùwà inú rere sí Jesu?

      12 Bí àwọn àgùntàn mìíràn bá ń wàásù ìhìn rere náà nísinsìnyí pẹ̀lú àwọn ẹni-àmì-òróró, tí wọ́n sì ń ṣèrànwọ́ fún wọn, èé ṣe tí wọn yóò fi béèrè pé: “Oluwa, nígbà wo ni awa rí ọ tí ebi ń pa ọ́ tí a sì bọ́ ọ, tabi tí òùngbẹ ń gbẹ ọ́, tí a sì fún ọ ní nǹkan lati mu?” (Matteu 25:37) Ìdí púpọ̀ ni ó lè wà. Òwe àkàwé ni èyí jẹ́. Nípa rẹ̀, Jesu fi ìdàníyàn rẹ̀ jíjinlẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa tẹ̀mí; àánú wọn ṣe é, ó jìyà pẹ̀lú wọn. Jesu ti sọ ṣáájú pé: “Ẹni tí ó bá gbà yín gbà mí pẹlu, ẹni tí ó bá sì gbà mí gba ẹni naa pẹlu tí ó rán mi jáde.” (Matteu 10:40) Nínú àkàwé yìí, Jesu nasẹ̀ ìlànà náà síwájú sí i, ní fífi hàn pé ohun tí a bá ṣe (ìbáà jẹ́ rere tàbí búburú) sí àwọn arákùnrin rẹ̀ ń dé ọ̀run pàápàá; ṣe ni ó dà bíi pé, a ṣe é sí i ní ọ̀run. Bákan náà, níhìn-ín, Jesu ń tẹnu mọ́ ọ̀pá ìdiwọ̀n Jehofa fún ṣíṣèdájọ́, ní mímú kí ó ṣe kedere pé ìdájọ́ Ọlọrun, yálà ó dáni láre tàbí ó dáni lẹ́bi, tọ́ ó sì yẹ. Àwọn ewúrẹ́ kò lè rí àwáwí ṣe pé, ‘Tóò, ká ní a ti rí ọ ní tààràtà ni.’

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́