-
Máa Ṣe Ohun Táá Jẹ́ Kí Àlàáfíà àti Ìṣọ̀kan Wà Nínú ÌjọGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
3. Kí lo lè ṣe tí èdèkòyédè bá wáyé láàárín ìwọ àti Kristẹni míì?
Òótọ́ ni pé a wà níṣọ̀kan, síbẹ̀ ó yẹ ká máa rántí pé aláìpé ni gbogbo wa. Nígbà míì, a lè ṣẹ ara wa tàbí ká ṣe ohun tó dun àwọn ẹlòmíì. Torí náà, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ fún wa pé “ẹ . . . máa dárí ji ara yín,” ó fi kún un pé: “Bí Jèhófà ṣe dárí jì yín ní fàlàlà, ẹ̀yin náà gbọ́dọ̀ máa ṣe bẹ́ẹ̀.” (Ka Kólósè 3:13.) Ọ̀pọ̀ ìgbà la ti ṣẹ Jèhófà tó sì ti dárí jì wá. Torí náà, ó fẹ́ káwa náà máa dárí ji ara wa. Tó o bá rí i pé o ti ṣẹ ẹnì kan, gbìyànjú láti lọ bá ẹni náà kẹ́ ẹ lè yanjú ọ̀rọ̀ náà.—Ka Mátíù 5:23, 24.b
-
-
Máa Ṣe Ohun Táá Jẹ́ Kí Àlàáfíà àti Ìṣọ̀kan Wà Nínú ÌjọGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, a máa ń ṣẹ àwọn míì. Kí ló yẹ ká ṣe tírú ẹ̀ bá ṣẹlẹ̀? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Nínú fídíò yẹn, àwọn nǹkan wo ni arábìnrin yẹn ṣe kó lè wá àlàáfíà?
-