-
Ṣé Wàá Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Nípa Jésù Mú Kó O Kọsẹ̀?Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021 | May
-
-
3 Jésù mọ̀ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ò ní gbà pé òun ni Mèsáyà. (Jòh. 5:39-44) Ó sọ fún àwọn kan lára àwọn ọmọlẹ́yìn Jòhánù Arinibọmi pé: “Aláyọ̀ ni ẹni tí kò rí ohunkóhun tó máa mú kó kọsẹ̀ nínú mi.” (Mát. 11:2, 3, 6) Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ ò fi tẹ́tí sí Jésù?
-
-
Ṣé Wàá Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Nípa Jésù Mú Kó O Kọsẹ̀?Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021 | May
-
-
(1) IBI TÍ JÉSÙ DÀGBÀ SÍ
Ọ̀pọ̀ kọsẹ̀ nítorí ibi tí Jésù dàgbà sí. Báwo lèyí ṣe lè mú káwọn èèyàn kọsẹ̀ lónìí? (Wo ìpínrọ̀ 5)b
5. Kí ló ṣeé ṣe kó fà á táwọn kan fi ronú pé Jésù kọ́ ni Mèsáyà?
5 Ọ̀pọ̀ ló kọsẹ̀ torí ibi tí Jésù dàgbà sí. Wọ́n gbà pé kò sí olùkọ́ bíi Jésù àti pé ó ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu. Àmọ́ lójú wọn, ọmọ káfíńtà lásánlàsàn ni. Yàtọ̀ síyẹn Násárẹ́tì ló ti wá, àwọn èèyàn ò sì ka ìlú yìí sí pàtàkì rárá. Kódà, Nàtáníẹ́lì tó pa dà wá di ọmọlẹ́yìn Jésù sọ nígbà kan pé: “Ṣé ohun rere kankan lè wá láti Násárẹ́tì?” (Jòh. 1:46) Ó lè jẹ́ torí pé Nàtáníẹ́lì kì í fojú gidi wo àwọn tó wá láti ìlú yẹn, ó sì lè jẹ́ pé àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Míkà 5:2 ló wà lọ́kàn ẹ̀ tó sọ pé Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ni wọ́n máa bí Mèsáyà náà sí, kì í ṣe Násárẹ́tì.
6. Kí ló yẹ kó mú kí àwọn èèyàn ìgbà yẹn gbà pé Jésù ni Mèsáyà?
6 Kí ni Ìwé Mímọ́ sọ? Wòlíì Àìsáyà sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn ọ̀tá Jésù kò ní fiyè sí ‘kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa ìran tí Mèsáyà’ ti wá. (Àìsá. 53:8) Bẹ́ẹ̀ sì rèé, gbogbo àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ yẹn ló wà lákọọ́lẹ̀. Ká sọ pé àwọn èèyàn yẹn fara balẹ̀ gbé àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ yẹn yẹ̀ wò ni, wọ́n á rí i pé Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ni wọ́n bí Jésù sí àti pé àtọmọdọ́mọ Ọba Dáfídì ni. (Lúùkù 2:4-7) Torí náà, ibi tí wọ́n bí Jésù sí bá àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Míkà 5:2 mu. Kí wá nìṣòro àwọn èèyàn náà? Ìṣòro wọn ni pé wọn ò ṣe ìwádìí dáadáa, wọn ò sì rídìí ọ̀rọ̀. Ìdí nìyẹn tí ọ̀pọ̀ wọn fi kọsẹ̀.
-
-
Ṣé Wàá Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Nípa Jésù Mú Kó O Kọsẹ̀?Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021 | May
-
-
(2) JÉSÙ KỌ̀ LÁTI FI ÀMÌ HÀN
Ọ̀pọ̀ kọsẹ̀ nítorí pé Jésù ò fi àmì hàn wọ́n. Báwo lèyí ṣe lè mú káwọn èèyàn kọsẹ̀ lónìí? (Wo ìpínrọ̀ 9-10)c
9. Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Jésù kọ̀ láti fi àmì hàn láti ọ̀run?
9 Àwọn kan nígbà ayé Jésù gbà pé ó mọ̀ọ̀yàn kọ́ gan-an. Àmọ́ ìyẹn nìkan ò tẹ́ wọn lọ́rùn. Wọ́n ní kó “fi àmì kan han àwọn láti ọ̀run” káwọn lè gbà pé òun ni Mèsáyà lóòótọ́. (Mát. 16:1) Ó lè jẹ́ àṣìlóye ohun tó wà nínú Dáníẹ́lì 7:13, 14 ló mú kí wọ́n sọ bẹ́ẹ̀. Bó ti wù kó rí, kì í ṣe àsìkò yẹn ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí nímùúṣẹ. Ohun tí Jésù fi ń kọ́ni ti tó láti mú kí wọ́n mọ̀ pé òun ni Mèsáyà. Àmọ́ nígbà tó kọ̀ láti fi àmì tí wọ́n béèrè hàn wọ́n, ṣe ni wọ́n kọsẹ̀.—Mát. 16:4.
10. Báwo ni Jésù ṣe mú ohun tí Àìsáyà sọ nípa Mèsáyà ṣẹ?
10 Kí ni Ìwé Mímọ́ sọ? Wòlíì Àìsáyà sọ nípa Mèsáyà pé: “Kò ní ké jáde tàbí kó gbé ohùn rẹ̀ sókè, kò sì ní jẹ́ ká gbọ́ ohùn rẹ̀ lójú ọ̀nà.” (Àìsá. 42:1, 2) Jésù ò pe àfiyèsí sí ara ẹ̀ nígbà tó ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni kò ṣe àṣehàn. Jésù ò bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ tẹ́ńpìlì tàbí kó wọ àwọn aṣọ oyè torí káwọn èèyàn lè gba tiẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni kò gbà káwọn èèyàn fi orúkọ oyè pe òun. Nígbà tí Jésù ń jẹ́jọ́ níwájú Ọba Hẹ́rọ́dù, kò ṣe iṣẹ́ àmì kó lè rí ojúure ọba náà. (Lúùkù 23:8-11) Òótọ́ ni pé Jésù ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu, àmọ́ iṣẹ́ ìwàásù ló kà sí pàtàkì jù. Ó tiẹ̀ sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn ẹ̀ pé: “Torí ìdí tí mo ṣe wá nìyí.”—Máàkù 1:38.
-