-
Ṣé Wàá Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Nípa Jésù Mú Kó O Kọsẹ̀?Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021 | May
-
-
(3) JÉSÙ Ò TẸ̀ LÉ Ọ̀PỌ̀ NÍNÚ ÀṢÀ ÀWỌN JÚÙ
Ọ̀pọ̀ kọsẹ̀ nítorí pé Jésù bẹnu àtẹ́ lu àwọn àṣà wọn kan. Báwo lèyí ṣe lè mú káwọn èèyàn kọsẹ̀ lónìí? (Wo ìpínrọ̀ 13)d
13. Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ fi bẹnu àtẹ́ lu Jésù?
13 Ó ya àwọn ọmọlẹ́yìn Jòhánù Arinibọmi lẹ́nu pé àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù kì í gbààwẹ̀. Jésù ṣàlàyé fún wọn pé kò sídìí tí àwọn ọmọlẹ́yìn òun fi máa gbààwẹ̀ nígbà tóun ṣì wà láyé. (Mát. 9:14-17) Yàtọ̀ síyẹn, àwọn Farisí àtàwọn alátakò Jésù bẹnu àtẹ́ lù ú torí pé kò tẹ̀ lé àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ wọn. Inú bí wọn nígbà tó wo àwọn èèyàn sàn lọ́jọ́ Sábáàtì. (Máàkù 3:1-6; Jòh. 9:16) Àwọn èèyàn yìí gbà pé àwọn ń pa Sábáàtì mọ́, bẹ́ẹ̀ sì rèé, wọn ò rí ohun tó burú nínú bí wọ́n ṣe ń ṣòwò nínú tẹ́ńpìlì. Wọ́n gbaná jẹ nígbà tí Jésù dẹ́bi fún wọn nítorí òwò tí wọ́n ń ṣe nínú tẹ́ńpìlì. (Mát. 21:12, 13, 15) Bákan náà, àwọn tí Jésù wàásù fún nínú sínágọ́gù tó wà ní Násárẹ́tì bínú gidigidi nígbà tó sọ ìtàn kan tó jẹ́ kó hàn gbangba pé onímọtara-ẹni-nìkan ni wọ́n, wọn ò sì nígbàgbọ́. (Lúùkù 4:16, 25-30) Ohun tí wọ́n retí pé kí Jésù ṣe àmọ́ tí ò ṣe mú kí ọ̀pọ̀ kọsẹ̀.—Mát. 11:16-19.
14. Kí nìdí tí Jésù fi dẹ́bi fún àwọn tó ń gbé àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ lárugẹ?
14 Kí ni Ìwé Mímọ́ sọ? Jèhófà gbẹnu wòlíì Àìsáyà sọ pé: “Àwọn èèyàn yìí ń fi ẹnu wọn sún mọ́ mi, wọ́n sì ń fi ètè wọn bọlá fún mi, àmọ́ ọkàn wọn jìnnà gan-an sí mi; àṣẹ èèyàn tí wọ́n kọ́ wọn ló sì ń mú kí wọ́n máa bẹ̀rù mi.” (Àìsá. 29:13) Ó tọ́, ó sì yẹ bí Jésù ṣe dẹ́bi fún àwọn àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu. Yàtọ̀ sí pé àwọn àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ yìí ò bá Ìwé Mímọ́ mu, ńṣe làwọn tó ń gbé wọn lárugẹ tún kọ Jèhófà àti Mèsáyà tó rán wá sáyé.
-
-
Ṣé Wàá Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Nípa Jésù Mú Kó O Kọsẹ̀?Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021 | May
-
-
(4) JÉSÙ Ò DÁ SÍ Ọ̀RỌ̀ ÒṢÈLÚ
Ọ̀pọ̀ kọsẹ̀ nítorí pé Jésù ò dá sọ́rọ̀ òṣèlú. Báwo lèyí ṣe lè mú káwọn èèyàn kọsẹ̀ lónìí? (Wo ìpínrọ̀ 17)e
17. Kí lọ̀pọ̀ èèyàn ń retí pé kí Jésù ṣe?
17 Nígbà ayé Jésù, ọ̀pọ̀ èèyàn ń wá bí wọ́n ṣe máa kúrò lábẹ́ àjàgà àwọn Róòmù, wọ́n sì retí pé Mèsáyà ló máa dá wọn nídè. Àmọ́ nígbà tí wọ́n fẹ́ fi Jésù jọba, ṣe ló kọ̀ jálẹ̀. (Jòh. 6:14, 15) Ẹ̀rù ń ba àwọn míì, títí kan àwọn àlùfáà pé Jésù fẹ́ gbé ìjọba kan kalẹ̀. Wọ́n gbà pé ìyẹn máa múnú bí àwọn ará Róòmù torí pé ìjọba Róòmù ti fún àwọn àlùfáà yẹn ní àṣẹ déwọ̀n àyè kan. Àwọn nǹkan yìí ló mú kí ọ̀pọ̀ àwọn Júù kọsẹ̀.
18. Àwọn àsọtẹ́lẹ̀ wo nípa Mèsáyà ni ọ̀pọ̀ ò fiyè sí?
18 Kí ni Ìwé Mímọ́ sọ? Òótọ́ ni pé ọ̀pọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ ló sọ pé Mèsáyà máa jẹ́ ajagunṣẹ́gun. Àmọ́, àwọn àsọtẹ́lẹ̀ míì sọ pé ó máa kọ́kọ́ kú fún ẹ̀ṣẹ̀ wa. (Àìsá. 53:9, 12) Kí wá nìdí tí àwọn Júù fi ní èrò tí ò tọ́ nípa Mèsáyà? Ìdí ni pé nígbà yẹn lọ́hùn-ún, ṣe lọ̀pọ̀ àwọn Júù máa ń gbójú fo àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó sọ pé Mèsáyà kò ní yanjú ìṣòro wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.—Jòh. 6:26, 27.
-