-
“Èmi Yóò Mú Kí Ọkàn Wọn Ṣọ̀kan”Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
11 Ní gbogbo àkókò tí kò sí ìmọ́lẹ̀ òtítọ́, táwọn oníṣọ́ọ̀ṣì sì ń lo agbára lórí àwọn èèyàn, àwọn kan wà tí wọ́n jẹ́ Kristẹni tòótọ́, ìyẹn àwọn “àlìkámà” tí Jésù sọ nínú àkàwé rẹ̀. Bíi ti àwọn Júù tó wà nígbèkùn, tí Ìsíkíẹ́lì 6:9 sọ nípa wọn, wọ́n rántí Ọlọ́run tòótọ́. Àwọn kan tiẹ̀ fìgboyà ta ko àwọn ẹ̀kọ́ èké tó kúnnú ṣọ́ọ̀ṣì. Àwọn èèyàn fi wọ́n ṣẹ̀sín, wọ́n sì ṣe inúnibíni sí wọn. Àmọ́, ṣé Jèhófà máa fi àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀ pátápátá nínú ìgbèkùn tẹ̀mí ni? Ká má rí i! Bíi ti ọ̀rọ̀ Ísírẹ́lì àtijọ́, Jèhófà fi ìbínú hàn dé ìwọ̀n tó yẹ, kò sì jẹ́ kó pẹ́ jù kí ìbínú náà tó rọlẹ̀. (Jer. 46:28) Yàtọ̀ síyẹn, Jèhófà ò fi àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀ láìní ìrètí. Ẹ jẹ́ ká wá pa dà sọ́dọ̀ àwọn Júù tó wà nígbèkùn ní Bábílónì àtijọ́, ká sì wo bí Jèhófà ṣe jẹ́ kí wọ́n nírètí pé wọ́n á bọ́ nígbèkùn lọ́jọ́ kan.
Ọ̀pọ̀ ọdún ni àwọn Kristẹni tòótọ́ fi dojú kọ inúnibíni látọ̀dọ̀ Bábílónì Ńlá (Wo ìpínrọ̀ 10 àti 11)
-