ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”—Kí Ni Jésù Ní Lọ́kàn?
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
    • ORÍ KÌÍNÍ

      “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”—Kí Ni Jésù Ní Lọ́kàn?

      Ọ̀dọ́kùnrin ọlọ́rọ̀ kan kúnlẹ̀, ó sì ń bi Jésù ní ìbéèrè

      “Kí ni mo gbọ́dọ̀ ṣe láti jogún ìyè àìnípẹ̀kun?”

      1, 2. Ìpè wo ló ṣe pàtàkì jù tí ẹ̀dá èèyàn èyíkéyìí lè rí gbà, ìbéèrè wo ló sì yẹ ká bi ara wa?

      ÈWO lára àwọn ìpè tó o tíì gbà rí lo kà sí pàtàkì jù lọ? Ó ṣeé ṣe kó o rántí ìgbà kan tí wọ́n pè ọ́ síbi ayẹyẹ pàtàkì kan, bóyá ìgbéyàwó àwọn kan tó o fẹ́ràn gidigidi. O sì lè rántí ọjọ́ tí wọ́n pè ọ́ pé kó o wá gba iṣẹ́ pàtàkì kan. Bó o bá ti gba irú ìpè bẹ́ẹ̀ rí, kò sí iyè méjì pé wàá rántí bí inú rẹ ṣe dùn tó lọ́jọ́ náà. Wàá sì tún rántí bó o ṣe gbà lọ́kàn ara rẹ pé kí wọ́n tó lè pè ọ́ sírú ibi bẹ́ẹ̀, ó ní láti jẹ́ pé wọ́n kà ọ́ sẹ́ni pàtàkì. Àmọ́, ní báyìí, ẹnì kan pè ọ́ sí ohun kan tó dáa jùyẹn lọ fíìfíì. Gbogbo wa pátá lẹni náà sì pè. A jẹ́ ìpè ọ̀hún o, a ò jẹ́ ẹ o, ó kàn wá gbọ̀ngbọ̀n. Ó jẹ́ ìpinnu tó ṣe pàtàkì jù lọ tá a ní láti ṣe nígbèésí ayé wa.

      2 Ìpè wo là ń sọ nípa rẹ̀ ná? Ìpè látọ̀dọ̀ Jésù Kristi tí í ṣe Ọmọ bíbí kan ṣoṣo ti Jèhófà Ọlọ́run Olódùmarè ni. Inú Bíbélì ni ìpè ọ̀hún wà. Nínú Mátíù 4:19, Jésù sọ níbẹ̀ pé: “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.” Jésù ń tipa gbólóhùn yìí pe olúkúlùkù wa. Ì bá dáa tí kálukú wa bá bi ara rẹ̀ pé, ‘Ṣé màá jẹ́ ìpè yìí?’ O lè máa rò pé ìdáhùn yẹn ò le, ta ló jẹ́ kọ irú ìpè pàtàkì bẹ́ẹ̀? Ṣùgbọ́n o jẹ́ mọ̀ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni ò kọbi ara sí ìpè yẹn. Kí ló lè fà á?

      3, 4. (a) Àwọn nǹkan wo tó fẹ́rẹ̀ẹ́ máà sẹ́ni tí kì í wù ló wà níkàáwọ́ ọkùnrin kan tó tọ Jésù lọ láti béèrè nípa bóun ṣe lè ní ìyè àìnípẹ̀kun? (b) Àwọn ànímọ́ rere wo ló ṣeé ṣe kí Jésù rí lára ọ̀dọ́kùnrin ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso náà?

      3 Wo àpẹẹrẹ ọkùnrin kan tí Jésù fúnra rẹ̀ nawọ́ irú ìpè tá à ń sọ yìí sí ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún méjì [2,000] ọdún sẹ́yìn. Ẹni-ò-sí-àjọ-ò-pé lọkùnrin náà. Ó kéré tán, ọkùnrin náà ní nǹkan mẹ́tà tó fẹ́rẹ̀ẹ́ máà sẹ́ni táwọn nǹkan náà kì í wù. Ọ̀dọ́ ni, ọlọ́rọ̀ ni, ó sì tún wà nípò àṣẹ. Bíbélì pè é ní “ọ̀dọ́kùnrin,” ó sọ pé “ó ní ọrọ̀ gan-an” ó sì tún pè é ní “olùṣàkóso.” (Mátíù 19:20; Lúùkù 18:18, 23) Síbẹ̀, nǹkan kan ṣì wà tí kò yẹ ká gbójú fò dá lára ọ̀dọ́kùnrin yìí. Jésù, Àgbà Olùkọ́ náà ti wàásù ní etígbọ̀ọ́ ọkùnrin yìí rí, ohun tó gbọ́ sì wù ú.

      4 Èyí tó pọ̀ jù lọ lára àwọn olùṣàkóso ayé ìgbà yẹn ni kò ka Jésù kún ẹni tí wọ́n lè bọ̀wọ̀ fún. (Jòhánù 7:48; 12:42) Ṣùgbọ́n olùṣàkóso yìí ò fìwà jọ wọ́n. Ohun tí Bíbélì sọ fún wa nípa rẹ̀ ni pé: “Bí [Jésù] sì ti ń jáde lọ ní ọ̀nà rẹ̀, ọkùnrin kan sáré wá, ó sì wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bi í léèrè pé: ‘Olùkọ́ Rere, kí ni mo gbọ́dọ̀ ṣe láti jogún ìyè àìnípẹ̀kun?’” (Máàkù 10:17) Ó yẹ ká kíyè sí bó ṣe ń wu ọkùnrin yìí tó láti rí Jésù bá sọ̀rọ̀, ó gbé ìtìjú tà ó sì ń sáré tọ̀ ọ́ lẹ́yìn jànnà jànnà ní gbangba bíi ẹni tíṣòro bá. Yàtọ̀ síyẹn, nígbà tó bá Kristi, ńṣe ló kúnlẹ̀ wọ̀ọ̀ níwájú rẹ̀. Èyí fi hàn pé ó nírẹ̀lẹ̀ débì kan àti pé ó ń wù ú láti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run. Àwọn ànímọ́ rere tó ní yẹn wú Jésù lórí. (Mátíù 5:3; 18:4) A wá lè rí ìdí tí Jésù fi ní irú ìṣarasíhùwà tó ní sí i. Bíbélì sọ pé “Jésù wò ó, ó sì ní ìfẹ́ fún un.” (Máàkù 10:21) Báwo ni Jésù ṣe dáhùn ìbéèrè ọ̀dọ́kùnrin yìí?

      Ìpè Tó Ṣàrà Ọ̀tọ̀

      5. Ọ̀nà wo ni Jésù gbà fèsì ìbéèré ọ̀dọ́kùnrin ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso yìí, báwo la sì ṣe mọ̀ pé “ohun kan” tó kù nípa ọkùnrin náà kì í ṣe pé kó lọ di tálákà? (Tún wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)

      5 Jésù fi hàn pé ó pẹ́ tí Bàbá òun ti ṣàlàyé ohun téèyàn ní láti ṣe tó bá fẹ́ rí ìyè àìnípẹ̀kun. Ó sọ ohun tí Ìwé Mímọ́ sọ pé èèyàn gbọ́dọ̀ ṣe, ọkùnrin yìí sì fèsì pé gbogbo ohun tó wà nínú Òfin Mósè lòun ń tẹ̀ lé. Àmọ́ níwọ̀n bí Jésù ti ní òye tó jinlẹ̀ ju ti èèyàn èyíkéyìí lọ, ó ṣeé ṣe fún un láti rí ohun kan tó fara sin nípa ọkùnrin náà. (Jòhánù 2:25) Ó fòye gbé e pé ọkùnrin yìí ní ìṣòro ńlá kan tí kò ní jẹ́ kó lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó wá sọ fún un pé: “Ohun kan ni ó kù nípa rẹ.” Kí ni “ohun kan” yìí? Jésù ní: “Lọ, ta àwọn ohun tí o ní, kí o sì fi fún àwọn òtòṣì.” (Máàkù 10:21) Ṣé ohun tí Jésù ní lọ́kàn ni pé ó dìgbà téèyàn ò bá ní kọ́bọ̀ lápò kó tó lè sin Ọlọ́run? Ká má rí i.a Ohun kan tó ṣe pàtàkì gan-an ni Jésù fẹ́ fà yọ.

      6. Kí ni Jésù pe ọ̀dọ́kùnrin ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso yẹn pé kó wá máa ṣe, kí sì ni ohun tó ṣe fi hàn pé ó jọba lọ́kàn rẹ̀?

      6 Kí Jésù bàa lè mú kí ohun kan tó kù fún ọkùnrin yẹn ṣe kedere, ó fún un ní àǹfààní tó ṣàrà ọ̀tọ̀, ó ní: “Wá di ọmọlẹ́yìn mi.” Tiẹ̀ ro ọ̀rọ̀ yẹn wò ná, àní Ọmọ Ọlọ́run Gíga Jù Lọ pe ọkùnrin yẹn, lójúkojú, pé kó wá máa tọ òun lẹ́yìn! Jésù tún ṣèlérí fún un pé òun á san án lẹ́san kan tí kò lálàá rẹ̀ rí. Jésù ní: “Ìwọ yóò sì ní ìṣúra ní ọ̀run.” Ǹjẹ́ ọ̀dọ́kùnrin ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso yẹn jẹ́ ìpè pàtàkì yìí lójú ẹsẹ̀? Àkọsílẹ̀ náà sọ pé: “Ó banú jẹ́ nítorí àsọjáde náà, ó sì lọ pẹ̀lú ẹ̀dùn-ọkàn, nítorí ó ní ohun ìní púpọ̀.” (Máàkù 10:21, 22) Nítorí pé kò retí pé ohun tí Jésù máa fi fèsì nìyẹn, ọ̀rọ̀ Jésù yẹn fi ohun tó jẹ ẹ́ lógún jù hàn. Kò síyè méjì pé àwọn dúkìá tó ní pẹ̀lú agbára àti iyì tó so mọ́ ọn ló wà lórí ẹ̀mí rẹ̀. Ó mà ṣe o, ìfẹ́ tó ní fáwọn nǹkan wọ̀nyẹn ju ìfẹ́ tó ní fún Kristi lọ. Nítorí náà, ó hàn pé “ohun kan” tó kù ni pé kó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ nífẹ̀ẹ́ Jésù àti Jèhófà débi tó fi lè yááfì gbogbo nǹkan tó ní nítorí wọn. Ṣùgbọ́n nítorí pé kò nífẹ̀ẹ́ Jésù àti Jèhófà dé ibẹ̀ yẹn, ó kọ̀ láti jẹ́ ìpè tá ò rírú ẹ̀ rí yẹn! Ọ̀nà wo wá ni pípè tí Jésù pe ọkùnrin yìí gbà kàn ọ́?

      7. Kí nìdí tó fi yẹ kó dá wa lójú pé ìpè Jésù kàn wá lónìí?

      7 Ọkùnrin yẹn nìkan kọ́ ni Jésù pè; kò sì fi ìpè náà mọ sọ́dọ̀ àwọn èèyàn mélòó kan péré. Jésù sọ pé: “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó . . . máa tọ̀ mí lẹ́yìn nígbà gbogbo.” (Lúùkù 9:23) Kíyè sí i pé “ẹnikẹ́ni” ló lè máa tọ Kristi lẹ́yìn, bó bá ṣáà ti jẹ́ pé lóòótọ́ lẹni náà “fẹ́” tọ̀ ọ́ lẹ́yìn. Ọlọ́run ló máa ń fa ẹni tí ọkàn rẹ̀ bá pé pérépéré bẹ́ẹ̀ sọ́dọ̀ Ọmọ rẹ̀. (Jòhánù 6:44) Kì í ṣe àwọn ọlọ́rọ̀ nìkan, kì í ṣe kìkì àwọn tálákà, kì í ṣe àwọn ẹ̀yà kan tàbí orílẹ̀-èdè kan, kì í sì í ṣe kìkì àwọn kan tó ń gbé láyé nígbà yẹn nìkan ṣùgbọ́n gbogbo èèyàn ló ní àǹfààní láti jẹ́ ìpè Jésù. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Jésù yẹn pé “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn” kan ìwọ náà. Kí nìdí tó fi yẹ kó wù ọ́ láti máa tọ Kristi lẹ́yìn? Àti pé kí ló túmọ̀ sí láti máa tọ Jésù lẹ́yìn?

  • “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”—Kí Ni Jésù Ní Lọ́kàn?
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
    • a Jésù ò ní kí gbogbo ẹni tó bá fẹ́ máa tọ òun lẹ́yìn fi gbogbo dúkìá wọn tọrẹ. Òótọ́ ni pé ìgbà kan wà tó sọ bó ṣe máa nira tó fún ọlọ́rọ̀ láti wọ Ìjọba Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ó ṣàlàyé síwájú sí i pé: “Ohun gbogbo ṣeé ṣe fún Ọlọ́run.” (Máàkù 10:23, 27) Ó ṣe tán, àwọn ọlọ́rọ̀ mélòó kan wà lára àwọn tó di ọmọlẹ́yìn Kristi. Ńṣe ni ìjọ Kristẹni sì fún wọn ní ìmọ̀ràn nípa ọrọ̀, wọn ò ní kí wọ́n lọ fi gbogbo ọrọ̀ wọ́n tọrẹ fáwọn tálákà.—1 Tímótì 6:17.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́