-
Ǹjẹ́ Ó Yẹ Kó O Máa San Owó Orí?Jí!—2003 | December 8
-
-
Ronú ná lórí ohun tí Jésù sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀. Ó mọ̀ pé àwọn Júù bíi tirẹ̀ ní ìkórìíra gidigidi fún owó orí tí àwọn ará Róòmù máa ń bù lé wọn. Síbẹ̀, Jésù rọ̀ wọ́n pé: “Ẹ san àwọn ohun ti Késárì padà fún Késárì, ṣùgbọ́n àwọn ohun ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.” (Máàkù 12:17) Ó yẹ ká tún kíyè sí i pé, ìjọba náà gan-an tó máa pa Jésù láìpẹ́ sígbà yẹn ló rọ̀ wọ́n pé kí wọ́n máa san owó orí fún.
-
-
Ǹjẹ́ Ó Yẹ Kó O Máa San Owó Orí?Jí!—2003 | December 8
-
-
a Ìmọ̀ràn Jésù láti san “ohun ti Késárì . . . fún Késárì” kò túmọ̀ sí pé owó orí nìkan ṣoṣo la gbọ́dọ̀ san. (Mátíù 22:21) Ìwé náà, Critical and Exegetical Hand-Book to the Gospel of Matthew, látọwọ́ Heinrich Meyer, ṣàlàyé pé: “Kò yẹ ká lóye rẹ̀ pé gbólóhùn náà [ohun ti Késárì] . . . jẹ́ kìkì owó orí tó jẹ́ ojúṣe wa, bí kò ṣe gbogbo ohun tó bá jẹ́ ẹ̀tọ́ Késárì nítorí ìṣàkóso rẹ̀ tó bá òfin mu.”
-