-
Àwọn Ọjọ́ Ìkẹyìn Ha Nìyí Ní Ti Gidi Bí?Ilé Ìṣọ́—1997 | April 1
-
-
Àwọn Ọmọlẹ́yìn Jésù Béèrè Ìbéèrè Tí Ó Ní Láárí
Ẹnu ní láti ya àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù. Jésù ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ fún wọn tán, láìfọ̀rọ̀ bọpo bọyọ̀, pé a óò pa tẹ́ńpìlì àwòyanu Jerúsálẹ́mù run pátápátá! Irú àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ṣeni ní kàyéfì. Kò pẹ́ lẹ́yìn náà, bí wọ́n ti jókòó lórí Òkè Ólífì, mẹ́rin lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ bi Jésù pé: “Sọ fún wa, Nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀, kí ni yóò sì jẹ́ àmì wíwàníhìn-ín rẹ àti ti ìparí ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan?” (Mátíù 24:3; Máàkù 13:1-4) Bóyá wọ́n mọ̀ bẹ́ẹ̀, tàbí wọn kò mọ̀, ìdáhùn Jésù yóò ní ìmúṣẹ alápá méjì.
Ìparun tẹ́ńpìlì Jerúsálẹ́mù àti ìparí ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan ti àwọn Júù kì í ṣe ohun kan náà pẹ̀lú àkókò wíwàníhìn-ín Kristi àti ti ìparí ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan ti gbogbo àgbáyé. Síbẹ̀síbẹ̀, nínú ìdáhùn rẹ̀ gígùn, Jésù lo ìjáfáfá ní mímẹ́nu kan gbogbo apá wọ̀nyí tí ìbéèrè náà ní nínú. Ó sọ bí àwọn ipò nǹkan yóò ti rí ṣáájú ìparun Jerúsálẹ́mù fún wọn; ó tún sọ fún wọn bí ayé yóò ti rí nígbà wíwàníhìn-ín rẹ̀, nígbà tí òun yóò máa ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí Ọba ní ọ̀run, tí yóò sì wà ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ mímú gbogbo ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan ti ayé wá sí òpin.
Òpin Jerúsálẹ́mù
Lákọ̀ọ́kọ́, gbé ohun tí Jésù sọ nípa Jerúsálẹ́mù àti tẹ́ńpìlì rẹ̀ yẹ̀ wò ná. Ní èyí tí ó ju ọgbọ̀n ọdún ṣáájú àkókò yẹn, ó sọ tẹ́lẹ̀ nípa àkókò onínira ńlá fún ọ̀kan lára àwọn ìlú títóbi jù lọ lágbàáyé. Ní pàtàkì, kíyè sí àwọn ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí a kọ sílẹ̀ nínú Lúùkù 21:20, 21 pé: “Nígbà tí ẹ bá rí i tí àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun adótini bá yí Jerúsálẹ́mù ká, nígbà náà ni kí ẹ mọ̀ pé ìsọdahoro rẹ̀ ti sún mọ́lé. Nígbà náà ni kí àwọn wọnnì tí ń bẹ ní Jùdíà bẹ̀rẹ̀ sí í sá lọ sí àwọn òkè ńlá, kí àwọn wọnnì tí wọ́n sì wà ní àárín rẹ̀ fi ibẹ̀ sílẹ̀, kí àwọn wọnnì tí wọ́n sì wà ní àwọn ibi ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀.” Bí àwọn ọmọ ogun adótini yóò bá yí Jerúsálẹ́mù ká, báwo ni yóò ṣe ṣeé ṣe fún ‘àwọn tí wọ́n wà ní àárín rẹ̀’ láti “fi ibẹ̀ sílẹ̀,” gẹ́gẹ́ bí Jésù ti pàṣẹ? Ní kedere, Jésù ń dọ́gbọ́n sọ pé, àǹfààní kan yóò ṣí sílẹ̀. Ó ha ṣí sílẹ̀ bí?
Ní 66 Sànmánì Tiwa, ẹgbẹ́ ọmọ ogun Róòmù lábẹ́ àṣẹ Cestius Gallus, ti lé agbo ọmọ ogun Júù ọlọ̀tẹ̀ pa dà sí Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì ti há wọn mọ́ sáàárín ìlú náà. Àwọn ará Róòmù náà tilẹ̀ fi agbára wọ ìlú náà fúnra rẹ̀, wọ́n sì lọ jìnnà dé ibi ògiri tẹ́ńpìlì. Ṣùgbọ́n, lẹ́yìn náà, Gallus pàṣẹ fún ẹgbẹ́ ọmọ ogun rẹ̀ láti ṣe ohun kan tí ó múni ṣe kàyéfì gidigidi. Ó pàṣẹ fún wọn láti kógun pa dà! Àwọn sójà Júù tí wọ́n ti kún fáyọ̀ gbá tẹ̀ lé wọn, wọ́n sì ṣe jàǹbá fún àwọn ọmọ Róòmù ọ̀tá wọn tí ń sálọ. Nípa báyìí, àǹfààní tí Jésù sọ tẹ́lẹ̀ ṣí sílẹ̀. Àwọn Kristẹni tòótọ́ kọbi ara sí ìkìlọ̀ rẹ̀, wọ́n sì fi Jerúsálẹ́mù sílẹ̀. Ìpinnu tí ó mọ́gbọ́n dání ni èyí, nítorí pé, lẹ́yìn ọdún mẹ́rin péré, àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun Róòmù pa dà wá, tí Ọ̀gágun Titus sì ṣíwájú wọn. Lọ́tẹ̀ yí, kò sí àsálà kankan.
Àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun Róòmù yí Jerúsálẹ́mù ká lẹ́ẹ̀kan sí i; wọ́n fi àwọn òpó igi olórí ṣóńṣó ṣe odi yí i ká. Jésù ti sọ tẹ́lẹ̀ nípa Jerúsálẹ́mù pé: “Àwọn ọjọ́ náà yóò dé bá ọ nígbà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò kọ́ iṣẹ́ odi agbára yíká rẹ pẹ̀lú àwọn òpó igi olórí ṣóńṣó wọn yóò sì ká ọ mọ́ wọn yóò sì wàhálà rẹ láti ìhà gbogbo.”a (Lúùkù 19:43) Kò pẹ́ kò jìnnà, Jerúsálẹ́mù ṣubú; a sọ tẹ́ńpìlì ológo rẹ̀ di eérú. A ti mú ọ̀rọ̀ Jésù ṣẹ títí dórí bíńtín!
Ṣùgbọ́n, ohun tí Jésù ní lọ́kàn ju ìparun yẹn lórí Jerúsálẹ́mù lọ. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ti bi í nípa àmì wíwàníhìn-ín rẹ̀ pẹ̀lú. Wọn kò mọ̀ nígbà yẹn, ṣùgbọ́n èyí ń tọ́ka sí àkókò kan, nígbà tí a óò gbé e sórí oyè gẹ́gẹ́ bí Ọba ní ọ̀run. Kí ni ó sọ tẹ́lẹ̀?
-
-
Àwọn Ọjọ́ Ìkẹyìn Ha Nìyí Ní Ti Gidi Bí?Ilé Ìṣọ́—1997 | April 1
-
-
a Láìsí àní-àní, ọwọ́ Titus ròkè níhìn-ín. Síbẹ̀síbẹ̀, ní àwọn apá ṣíṣe pàtàkì méjì, kò ṣàṣeparí ohun tí ó ń fẹ́. Ó fún wọn láǹfààní jíjuwọ́sílẹ̀ ní wọ́ọ́rọ́wọ́, ṣùgbọ́n lọ́nà tí ó ṣeni ní kàyéfì, àwọn olórí ìlú fàáké kọ́rí pátápátá. Nígbà tí wọ́n sì fọ́ ògiri ìlú náà lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, ó pàṣẹ pé kí wọ́n má ṣe fọwọ́ kan tẹ́ńpìlì náà. Síbẹ̀síbẹ̀, a jó o run pátápátá! Àsọtẹ́lẹ̀ Jésù ti mú un ṣe kedere pé, a óò sọ Jerúsálẹ́mù di ahoro, a óò sì pa tẹ́ńpìlì rẹ̀ run pátápátá.—Máàkù 13:1, 2.
-