ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Kí Òǹkàwé Lo Ìfòyemọ̀”
    Ilé Ìṣọ́—1999 | May 1
    • 18, 19. Kí ni àwọn ìdí táa fún wa tó fi hàn pé ‘sísa lọ sórí òkè ńlá’ kò ní túmọ̀ sí títi inú ẹ̀sìn kan bọ́ sí òmíràn?

      18 Lẹ́yìn tó ti sọ tẹ́lẹ̀ nípa ‘dídúró tí ohun ìríra náà yóò dúró ní ibi mímọ́,’ Jésù kìlọ̀ fún àwọn olóye láti máà jáfara. Ṣé ohun tí ó ń sọ ni pé nígbà tí àkókò ti lọ tán yẹn—nígbà tí “ohun ìríra” ti “dúró ní ibi mímọ́”—ọ̀pọ̀ èèyàn yóò sá kúrò nínú ìsìn èké lọ sínú ìsìn tòótọ́? Kò dájú. Ṣàgbéyẹ̀wò ìmúṣẹ àkọ́kọ́. Jésù wí pé: “Kí àwọn tí ń bẹ ní Jùdíà bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ sí àwọn òkè ńlá. Kí ẹni tí ó wà ní orí ilé má ṣe sọ̀ kalẹ̀, tàbí kí ó wọlé lọ mú ohunkóhun jáde kúrò nínú ilé rẹ̀; kí ẹni tí ó wà ní pápá má sì padà sí àwọn ohun tí ń bẹ lẹ́yìn láti mú ẹ̀wù àwọ̀lékè rẹ̀. Ègbé ni fún àwọn obìnrin tí ó lóyún àti àwọn tí ń fi ọmú fún ọmọ ọwọ́ ni ọjọ́ wọnnì! Ẹ máa gbàdúrà kí ó má ṣẹlẹ̀ ní ìgbà òtútù.”—Máàkù 13:14-18.

  • “Kí Òǹkàwé Lo Ìfòyemọ̀”
    Ilé Ìṣọ́—1999 | May 1
    • 22. Kí ni fífi táa bá fi ìmọ̀ràn Jésù nípa sísálọ sórí òkè sílò lè ní nínú?

      22 Ní báyìí, a kò lè mọ gbogbo kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa ìpọ́njú ńlá, ṣùgbọ́n ó bọ́gbọ́n mu fún wa láti dé ìparí èrò pé ní tiwa, sísá tí Jésù sọ kò ní jẹ́ sísá láti àgbègbè kan lọ sí àgbègbè mìíràn. Ní lọ́ọ́lọ́ọ́, àwọn èèyàn Ọlọ́run ti wà káàkiri àgbáyé, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ máà sí ibi tí wọn ò sí. Ṣùgbọ́n o, ká jẹ́ kó dá wa lójú pé, nígbà tó bá pọndandan pé kí àwọn Kristẹni sá, sísá wọn yóò jẹ́ bíbá a nìṣó láti di ìdúró wọn gédégbé mú ní ti pé wọ́n yàtọ̀ pátápátá sí àwọn ètò ìsìn èké. Ó tún ṣe pàtàkì pé Jésù kìlọ̀ pé kéèyàn má padà lọ sílé rẹ̀ torí pé ó fẹ́ lọ mú ẹ̀wù àwọ̀lékè tàbí torí àwọn ẹrù mìíràn tó fẹ́ gbé. (Mátíù 24:17, 18) Nítorí náà, àdánwò lè wà níwájú nípa ojú táa fi ń wo ọrọ̀ àlùmọ́nì; ṣé àwọn nǹkan yẹn la kà sí ohun to ṣe pàtàkì jù lọ, àbí ìgbàlà tí yóò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá? Bẹ́ẹ̀ ni, sísá wa lè ní àwọn ìnira àti ìṣòro kan nínú. A ní láti múra tán láti ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn akẹgbẹ́ wa ní ọ̀rúndún kìíní ti ṣe, àwọn tí wọ́n sá kúrò ní Jùdíà lọ sí Pèríà, níkọjá Jọ́dánì.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́