-
Ará Samáríà Kan Jẹ́ Aládùúgbò RereIlé Ìṣọ́—1998 | July 1
-
-
Bí ọ̀ràn náà ṣe wá rí yìí, ọ̀rọ̀ tí Jésù bá ọkùnrin kan tí ó jẹ́ ògbóǹkangí nínú òfin àwọn Júù sọ kún fún ẹ̀kọ́. Ọkùnrin náà tọ Jésù wá, ó sì bi í pé: “Olùkọ́, nípa ṣíṣe kí ni èmi yóò fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” Ní fífèsì, Jésù pe àfiyèsí rẹ̀ sí Òfin Mósè, tí ó pàṣẹ pé kí a ‘nífẹ̀ẹ́ Jèhófà pẹ̀lú gbogbo ọkàn-àyà, gbogbo ọkàn, gbogbo okun, àti gbogbo èrò inú,’ kí a sì ‘nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò wa gẹ́gẹ́ bí ara wa.’ Amòfin náà wá bi Jésù pé: “Ní ti gidi ta ni aládùúgbò mi?” (Lúùkù 10:25-29; Léfítíkù 19:18; Diutarónómì 6:5) Gẹ́gẹ́ bí àwọn Farisí ti sọ, àwọn tí ń pa òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn Júù mọ́ ni a lo ọ̀rọ̀ náà “aládùúgbò” fún—dájúdájú kì í ṣe fún àwọn Kèfèrí tàbí àwọn ará Samáríà. Bí amòfin atọpinpin yìí bá rò pé Jésù yóò kín ojú ìwòye yẹn lẹ́yìn, ohun tí yóò gbọ́ yóò yà á lẹ́nu.
-
-
Ará Samáríà Kan Jẹ́ Aládùúgbò RereIlé Ìṣọ́—1998 | July 1
-
-
Ẹ̀kọ́ Àríkọ́gbọ́n
Ọkùnrin tí ń bi Jésù ní ìbéèrè ṣe bẹ́ẹ̀ láti lè “fi ara rẹ̀ hàn ní olódodo.” (Lúùkù 10:29) Bóyá ó rò pé Jésù yóò gbóríyìn fún òun fún rírọ̀ tí òun rọ̀ pinpin mọ́ Òfin Mósè. Ṣùgbọ́n ó yẹ kí ọ̀gbẹ́ni tí ó jọ ara rẹ̀ lójú yìí mọ̀ pé òtítọ́ ni òwe Bíbélì tí ó sọ pé: “Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dúró ṣánṣán lójú ara rẹ̀, ṣùgbọ́n Jèhófà ni ó ń díwọ̀n àwọn ọkàn-àyà.”—Òwe 21:2.
-