-
Sin Jèhófà Láìsí Ìpínyà ỌkànIlé Ìṣọ́—2015 | October 15
-
-
“Màríà . . . ń fetí sí ọ̀rọ̀ [Jésù]. Màtá . . . ní ìpínyà-ọkàn nítorí bíbójútó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ojúṣe.”—LÚÙKÙ 10:39, 40.
-
-
Sin Jèhófà Láìsí Ìpínyà ỌkànIlé Ìṣọ́—2015 | October 15
-
-
3, 4. Ọ̀nà wo ni Màríà gbà yan “ìpín rere,” kí ló sì dájú pé Màtá rí kọ́ nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ náà? (Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí.)
3 Jésù mọrírì bí Màtá àti Màríà ṣe gbà á lálejò, torí náà ó kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ pàtàkì látinú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Màríà lo àǹfààní yẹn láti gba ìmọ̀ látọ̀dọ̀ Olùkọ́ Ńlá náà, ó jókòó “lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa . . . ó sì ń fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.” Ohun tó yẹ kí Màtá náà ṣe nìyẹn. Ó sì dájú pé tó bá ṣe bẹ́ẹ̀, Jésù á gbóríyìn fún un pé kì í ṣe oúnjẹ tó ń gbọ́ nìkan ló gbájú mọ́.
-