-
Jèhófà Ń fi “Ẹ̀mí Mímọ́ Fún Àwọn Tí Ń béèrè Lọ́wọ́ Rẹ̀”Ilé Ìṣọ́—2006 | December 15
-
-
4 Jésù sọ pé: “Ta ni nínú yín tí yóò ní ọ̀rẹ́ kan, tí yóò sì lọ bá a ní ọ̀gànjọ́ òru, tí yóò sì wí fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù búrẹ́dì mẹ́ta, nítorí pé ọ̀rẹ́ mi kan ṣẹ̀ṣẹ̀ dé sọ́dọ̀ mi láti ìrìn àjò, èmi kò sì ní nǹkan kan láti gbé ka iwájú rẹ̀’? Tí ẹni yẹn láti inú ilé sì sọ ní ìfèsìpadà pé, ‘Yé dà mí láàmú. Ilẹ̀kùn ti wà ní títì pa, àwọn ọmọ mi kéékèèké sì wà pẹ̀lú mi lórí ibùsùn; èmi kò lè dìde kí n sì fún ọ ní ohunkóhun.’ Mo sọ fún yín, Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì yóò dìde, kí ó sì fún un ní ohunkóhun nítorí pé ó jẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, dájúdájú, nítorí ìtẹpẹlẹ rẹ̀ aláìṣojo, yóò dìde, yóò sì fún un ní àwọn ohun tí ó nílò.” Lẹ́yìn tí Jésù sọ àpèjúwe yìí, ó wá sọ ẹ̀kọ́ tá a lè rí kọ́ látinú rẹ̀ tó bá kan ọ̀rọ̀ àdúrà gbígbà, ó ní: “Ní ìbámu pẹ̀lú èyí, mo wí fún yín, Ẹ máa bá a nìṣó ní bíbéèrè, a ó sì fi í fún yín; ẹ máa bá a nìṣó ní wíwá kiri, ẹ ó sì rí; ẹ máa bá a nìṣó ní kíkànkùn, a ó sì ṣí i fún yín. Nítorí pé olúkúlùkù ẹni tí ń béèrè ń rí gbà, àti olúkúlùkù ẹni tí ń wá kiri ń rí, olúkúlùkù ẹni tí ó sì ń kànkùn ni a óò ṣí i fún.”—Lúùkù 11:5-10.
-
-
Jèhófà Ń fi “Ẹ̀mí Mímọ́ Fún Àwọn Tí Ń béèrè Lọ́wọ́ Rẹ̀”Ilé Ìṣọ́—2006 | December 15
-
-
6. Nígbà ayé Jésù, irú ọwọ́ wo làwọn èèyàn fi mú ọ̀rọ̀ àlejò ṣíṣe?
6 Jésù jẹ́ ká mọ̀ pé ńṣe ló yẹ ká máa fi àìṣojo tẹpẹlẹ mọ́ àdúrà gbígbà. Àmọ́ yàtọ̀ síyẹn, ó tún jẹ́ ká mọ ìdí tó fi yẹ ká máa ṣe bẹ́ẹ̀. Kí kókó yìí lè yé wa dáadáa, ẹ jẹ́ ká wo irú ọwọ́ táwọn tó gbọ́ àpèjúwe Jésù nípa ọkùnrin tó tẹpẹlẹ mọ́ bíbéèrè ohun tó ń fẹ́ yìí fi mú ọ̀rọ̀ àlejò ṣíṣe. Ọ̀pọ̀ ìtàn tó wà nínú Ìwé Mímọ́ ló fi hàn pé láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ́ Bíbélì, àwọn èèyàn fọwọ́ pàtàkì mú ọ̀rọ̀ àlejò ṣíṣe, pàápàá àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run. (Jẹ́nẹ́sísì 18:2-5; Hébérù 13:2) Nǹkan ìtìjú gbáà ló jẹ́ tí àlejò bá dé sọ́dọ̀ ẹnì kan tí onítọ̀hún ò sì ṣe é lálejò. (Lúùkù 7:36-38, 44-46) Ẹ jẹ́ ká fi kókó yẹn sọ́kàn bá a ṣe fẹ́ padà sórí àpèjúwe Jésù.
7. Kí nìdí tójú ò fi ti ẹni tó gbàlejò nínú àpèjúwe tí Jésù sọ yìí láti jí ọ̀rẹ́ ẹ̀ lójú oorun?
7 Ọ̀gànjọ́ òru ni àlejò dé sílé ọkùnrin tí Jésù mẹ́nu kàn nínú àpèjúwe yìí. Ọkùnrin náà rí i pé òun gbọ́dọ̀ pèsè oúnjẹ fún àlejò òun, àmọ́ kò ní “nǹkan kan láti gbé ka iwájú rẹ̀.” Ó wò ó pé àlejò pàjáwìrì mà rèé! Ó wá di pé kó ṣe gbogbo ohun tó bá lè ṣe láti rí i pé òun fún àlejò òun ní oúnjẹ jẹ. Bó ṣe gbọ̀nà ilé ọ̀rẹ́ rẹ̀ lọ nìyẹn, kò sì tijú rárá láti jí i lójú oorun. Ó ní: “Ọ̀rẹ́, yá mi ní ìṣù búrẹ́dì mẹ́ta.” Ó bẹ ọ̀rẹ́ ẹ̀ títí tíyẹn fi fún un lóhun tó ń béèrè. Ìgbà tó rí búrẹ́dì mú lọ sílé ló tó lè ṣe ojúṣe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹni tó gbàlejò.
Bí NǹKan Bá Ṣe Ṣe Pàtàkì Sí La Ṣe Ń Béèrè fún Un
8. Kí ni yóò jẹ́ ká lè tẹpẹlẹ mọ́ gbígbàdúrà pé kí Ọlọ́run fún wa ní ẹ̀mí mímọ́?
8 Kí ni àpèjúwe yìí fi hàn nípa ìdí tó fi yẹ ká tẹpẹlẹ mọ́ àdúrà gbígbà? Ọkùnrin náà ò yéé bẹ ọ̀rẹ́ rẹ̀ pé kó fóun ní búrẹ́dì nítorí ó mọ̀ pé kóun tó lè ṣe ojúṣe òun gẹ́gẹ́ bí ẹni tó gbàlejò, òun gbọ́dọ̀ ní búrẹ́dì. (Aísáyà 58:5-7) Láìsí búrẹ́dì, kò ní lè ṣe ojúṣe rẹ̀ dáadáa. Àwa Kristẹni tòótọ́ náà mọ̀ pé láti lè máa ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa lọ, ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ṣe pàtàkì ó ṣe kókó, ìdí nìyẹn tá ò yéé gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀. (Sekaráyà 4:6) Láìsí ẹ̀mí mímọ́, a ò ní lè ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa. (Mátíù 26:41) Ǹjẹ́ o rí ẹ̀kọ́ pàtàkì tá a lè rí kọ́ látinú àpèjúwe yìí? Tá a bá wo ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ohun kòṣeémáàní, a óò máa tẹpẹlẹ mọ́ bíbéèrè fún un.
9, 10. (a) Sọ àpèjúwe kan láti jẹ́ ká mọ ìdí tó fi yẹ ká tẹpẹlẹ mọ́ gbígbàdúrà fún ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run. (b) Ìbéèrè wo ló yẹ ká bi ara wa, kí sì nìdí?
9 Ẹ jẹ́ ká lo àpèjúwe ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lóde òní láti fi gbé ẹ̀kọ́ yẹn yọ. Ká sọ pé àìsàn dédé kọ lu ẹnì kan nínú ìdílé rẹ láàjìn òru. Ǹjẹ́ o ò ní wá dókítà lọ kó lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Tí àìsàn ọ̀hún kò bá le jù, o lè má ṣe bẹ́ẹ̀. Àmọ́, tó bá jẹ́ pé ńṣe lonítọ̀hún dá kú, ó dájú pé o ò ní tijú láti jí dókítà. Kí nìdí? Ìdí ni pé ọ̀ràn pàjáwìrì tó la ẹ̀mí lọ ni. O rí i pé o gbọ́dọ̀ jí dókítà lóru yẹn kó lè bá ẹ tọ́jú rẹ̀. Tí o kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹni náà lè kú. Lọ́nà kan náà, àwa Kristẹni tòótọ́ wà nínú ipò pàjáwìrì kan. Sátánì ń lọ káàkiri bíi “kìnnìún tí ń ké ramúramù,” ó ń wá ọ̀nà láti pa wá jẹ. (1 Pétérù 5:8) Tá ò bá sì fẹ́ kú nípa tẹ̀mí, a gbọ́dọ̀ ní ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run. Tá ò bá béèrè fún un, ohun tó léwu gan-an là ń ṣe yẹn. Nítorí náà, ó yẹ ká máa fi àìṣojo tẹpẹlẹ mọ́ gbígbàdúrà sí Ọlọ́run pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀. (Éfésù 3:14-16) Tá a bá ń gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ yìí nìkan la ó fi lè ní okun tá a fi máa “fara dà á dé òpin.”—Mátíù 10:22; 24:13.
-