ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ǹjẹ́ o ‘Ní Ọrọ̀ Lọ́dọ̀ Ọlọ́run’?
    Ilé Ìṣọ́—2007 | August 1
    • 7. Kí ni ọkùnrin inú àkàwé Jésù ṣe nípa ìṣòro tó ní?

      7 Ẹ jẹ́ ká padà sórí àkàwé Jésù yẹn wàyí. Kí ni ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà ṣe nígbà tí ilẹ̀ rẹ̀ mú ohun tó pọ̀ yanturu jáde débi pé kò ríbi kó àwọn ohun tó kórè náà sí? Ó pinnu láti wó àwọn ilé ìtọ́jú nǹkan pa mọ́ sí rẹ̀ lulẹ̀ kó sì kọ́ àwọn tó tóbi ju ti tẹ́lẹ̀ lọ kó lè ríbi kó gbogbo ọkà àtàwọn ohun rere rẹ̀ tó pọ̀ lápọ̀jù sí. Ìpinnu tó ṣe yẹn fi í lọ́kàn balẹ̀ gan-an ó sì fún un láyọ̀ débi pé ó ń sọ nínú ara rẹ̀ pé: “Èmi yóò sọ fún ọkàn mi pé: ‘Ọkàn, ìwọ ní ọ̀pọ̀ ohun rere tí a tò jọ pa mọ́ fún ọ̀pọ̀ ọdún; fara balẹ̀ pẹ̀sẹ̀, máa jẹ, máa mu, máa gbádùn.’”—Lúùkù 12:19.

      Kí Nìdí Tí Ọkùnrin Náà Fi Jẹ́ “Aláìlọ́gbọ́n-Nínú”?

      8. Ohun pàtàkì wo ni ọkùnrin inú àkàwé Jésù yìí gbójú fò dá?

      8 Àmọ́ gẹ́gẹ́ bí Jésù ṣe sọ ọ́, ohun tí ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà pinnu láti ṣe yìí kò fún un ní ìfọ̀kànbalẹ̀ tó rò pé òun máa ní. Ó lè dà bíi pé ohun tó fẹ́ ṣe yìí bọ́gbọ́n mu lóòótọ́ o, àmọ́ kò fi ohun pàtàkì kan kún un, ìyẹn ohun tí Ọlọ́run fẹ́. Tara rẹ̀ nìkan ló ń rò, ó ń ronú bóun á ṣe fara balẹ̀ pẹ̀sẹ̀, tóun á máa jẹ́, tóun á máa mu, tóun á sì máa gbádùn ara òun. Ó ti gbà pé níwọ̀n bóun ti ní “ọ̀pọ̀ ohun rere,” òun á tún wà láàyè fún “ọ̀pọ̀ ọdún.” Àmọ́, ó mà ṣe o, ibi tó fojú sí ọ̀nà ò gbabẹ̀. Bí Jésù ṣe sọ níṣàájú gẹ́ẹ́ lọ̀rọ̀ ọkùnrin náà rí, ó sọ pé “nígbà tí ẹnì kan bá tilẹ̀ ní ọ̀pọ̀ yanturu pàápàá, ìwàláàyè rẹ̀ kò wá láti inú àwọn ohun tí ó ní.” (Lúùkù 12:15) Òru ọjọ́ yẹn gan-an ni gbogbo ohun tí ọkùnrin náà tìtorí rẹ̀ ń ṣiṣẹ́ wá sópin lójijì, nítorí pé Ọlọ́run sọ fún un pé: “Aláìlọ́gbọ́n-nínú, òru òní ni wọn yóò fi dandan béèrè ọkàn rẹ lọ́wọ́ rẹ. Ta ni yóò wá ni àwọn ohun tí ìwọ tò jọ pa mọ́?”—Lúùkù 12:20.

  • Ǹjẹ́ o ‘Ní Ọrọ̀ Lọ́dọ̀ Ọlọ́run’?
    Ilé Ìṣọ́—2007 | August 1
    • 10. Kí nìdí tí níní “ọ̀pọ̀ ohun rere” kò fi ń ṣe ẹ̀rí pé èèyàn máa wà láàyè fún “ọ̀pọ̀ ọdún”?

      10 Á dára ká fi ẹ̀kọ́ inú àkàwé yìí sọ́kàn. Ṣé àwa náà ò dà bí ọkùnrin inú àkàwé yìí, ìyẹn ni pé ká ṣiṣẹ́ àṣekára láti rí i dájú pé a ní “ọ̀pọ̀ ohun rere” síbẹ̀ ká kùnà láti ṣe ohun tó máa jẹ́ ká nírètí àtiwà láàyè fún “ọ̀pọ̀ ọdún”? (Jòhánù 3:16; 17:3) Bíbélì sọ pé: “Àwọn ohun tí ó níye lórí kì yóò ṣàǹfààní rárá ní ọjọ́ ìbínú kíkan,” àti pé “ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀ rẹ̀—òun fúnra rẹ̀ yóò ṣubú.” (Òwe 11:4, 28) Nítorí náà, Jésù wá fi ọ̀rọ̀ ìṣílétí tó kẹ́yìn yìí kún àkàwé náà, ó ní: “Bẹ́ẹ̀ ni ó máa ń rí fún ẹni tí ó bá ń to ìṣúra jọ pa mọ́ fún ara rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kò ní ọrọ̀ síhà ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”—Lúùkù 12:21.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́